Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Kronika Keji 26:17-23 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Ṣugbọn Asaraya, alufaa, wọlé lọ bá a pẹlu àwọn ọgọrin alufaa tí wọ́n jẹ́ akọni.

18. Wọ́n dojú kọ ọ́, wọ́n ní, “Usaya, kò tọ́ fún ọ láti sun turari sí OLUWA; iṣẹ́ àwọn alufaa tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni ni, àwọn tí a ti yà sọ́tọ̀ láti máa sun turari. Jáde kúrò ninu ibi mímọ́! Nítorí o ti ṣe ohun tí kò tọ́, kò sì buyì kún ọ lọ́dọ̀ OLUWA Ọlọrun rẹ.”

19. Inú bí Usaya nítorí pé àwo turari ti wà lọ́wọ́ rẹ̀ tí ó fẹ́ fi sun turari. Níbi tí ó ti ń bínú sí àwọn alufaa, àrùn ẹ̀tẹ̀ yọ níwájú rẹ̀, lójú àwọn alufaa ninu ilé OLUWA.

20. Nígbà tí Asaraya, olórí alufaa ati àwọn alufaa rí i tí ẹ̀tẹ̀ yọ níwájú rẹ̀, wọ́n yára tì í jáde. Ìkánjú ni òun pàápàá tilẹ̀ bá jáde, nítorí pé OLUWA ti jẹ ẹ́ níyà.

21. Usaya ọba di adẹ́tẹ̀ títí ọjọ́ ikú rẹ̀. Ọ̀tọ̀ ni wọ́n kọ́ ilé fún un tí ó ń dá gbé; nítorí wọ́n yọ ọ́ kúrò ninu ilé OLUWA. Jotamu ọmọ rẹ̀ di alákòóso ìjọba, ó sì ń darí àwọn ará ìlú.

22. Àwọn nǹkan yòókù tí Usaya ṣe, láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin, wà ninu àkọsílẹ̀ wolii Aisaya, ọmọ Amosi.

23. Nígbà tí Usaya kú, wọ́n sin ín sí itẹ́ àwọn ọba, wọn kò sin ín sinu ibojì àwọn ọba, nítorí wọ́n ní, “Adẹ́tẹ̀ ni.” Jotamu ọmọ rẹ̀ sì jọba lẹ́yìn rẹ̀.

Ka pipe ipin Kronika Keji 26