Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 6:4-10 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Wọn yóo sì wí pé, “Ẹ múra kí á bá a jagun;ẹ dìde kí á lè kọlù ú lọ́sàn-án gangan!”Wọn óo tún sọ pé, “A gbé! Nítorí pé ọjọ́ ti lọ,ilẹ̀ sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ṣú!

5. Ẹ dìde kí á lè kọlù ú, lóru;kí á wó àwọn ilé ìṣọ́ rẹ̀ lulẹ̀!”

6. Nítorí pé OLUWA àwọn ọmọ ogun ti pàṣẹ fún àwọn ọ̀tá pé:“Ẹ gé àwọn igi tí ó yí Jerusalẹmu ká lulẹ̀;kí ẹ fi mọ òkítì kí ẹ sì dótì í.Dandan ni kí n fi ìyà jẹ ìlú náà,nítorí kìkì ìwà ìninilára ló kún inú rẹ̀.

7. Bí omi ṣé ń sun jáde ninu kànga,bẹ́ẹ̀ ni ibi ń sun ní Jerusalẹmu.Ìròyìn ìwà ipá ati ti jàgídíjàgan ń kọlura wọn ninu rẹ̀,àìsàn ati ìpalára ni à ń rí níbẹ̀ nígbà gbogbo.

8. Ẹ̀yin ará Jerusalẹmu! Ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ tí mò ń ṣe fun yín,bí bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi pẹlu yín óo pínyà,n óo sì sọ Jerusalẹmu di ahoro,ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé ibẹ̀ mọ́.”

9. OLUWA àwọn ọmọ ogun ní:“Ẹ ṣa àwọn ọmọ Israẹli yòókù jọ,bí ìgbà tí eniyan bá ń ṣa èso àjàrà tókù lẹ́yìn ìkórè.Tún dá ọwọ́ pada sẹ́yìn, kí o fi wọ́ ara àwọn ẹ̀ka,bí ẹni tí ń ká èso àjàrà.”

10. Mo ní, “Ta ni kí n bá sọ̀rọ̀, tí yóo gbọ́?Ta ni kí n kìlọ̀ fún tí yóo gbà?Etí wọn ti di, wọn kò lè gbọ́ràn mọ́.Ọ̀rọ̀ OLUWA ń rùn létí wọn,wọn kò fẹ́ gbọ́ mọ́.

Ka pipe ipin Jeremaya 6