Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 51:24-40 BIBELI MIMỌ (BM)

24. OLUWA ní,“Níṣojú yín ni n óo fi san ẹ̀san fún Babiloni,ati gbogbo àwọn tí wọn ń gbé Kalidea,fún gbogbo ibi tí wọ́n ṣe sí Sioni;èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

25. Wò ó! Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè ìparun,tí ò ń pa gbogbo ayé run.N óo gbá ọ mú, n óo tì ọ́ lulẹ̀ láti orí àpáta,n óo sì sọ ọ́ di òkè tí ó jóná.

26. Wọn kò ní rí òkúta kan mú jáde ninu rẹ,tí eniyan lè fi ṣe òkúta igun ilé;tabi tí wọn lè fi ṣe ìpìlẹ̀ ilé,ń ṣe ni o óo wó lulẹ̀ títí ayé.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

27. “Ẹ ta àsíá sórí ilẹ̀ ayé,ẹ fun fèrè ogun láàrin àwọn orílẹ̀-èdè;kí àwọn orílẹ̀-èdè múra láti gbógun tì í,ẹ sì pe àwọn ìjọba jọ láti dojú kọ ọ́;àwọn ìjọba orílẹ̀-èdè bíi Ararati, Minni, ati Aṣikenasi.Ẹ yan balogun tí yóo gbógun tì í;ẹ kó ẹṣin wá, kí wọn pọ̀ bí eṣú.

28. Kí àwọn orílẹ̀-èdè múra láti gbógun tì í,kí àwọn ọba ilẹ̀ Media múra, pẹlu àwọn gomina wọn,ati àwọn ẹmẹ̀wà wọn,ati gbogbo ilẹ̀ tí ó wà lábẹ́ wọn.

29. Jìnnìjìnnì bo gbogbo ilẹ̀ náà,wọ́n wà ninu ìrora,nítorí pé OLUWA kò yí ìpinnu rẹ̀ lórí Babiloni pada,láti sọ ilẹ̀ náà di ahoro,láìsí ẹnìkan kan ninu rẹ̀ mọ́.

30. Àwọn ọmọ ogun Babiloni ti ṣíwọ́ ogun jíjà,wọ́n wà ní ibi ààbò wọn;àárẹ̀ ti mú wọn, wọ́n sì ti di obinrin.Àwọn ilé inú rẹ̀ ti ń jóná,àwọn ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ sì ti ṣẹ́.

31. Àwọn tí ń sáré ń pàdé ara wọn lọ́nà,bẹ́ẹ̀ ni àwọn ikọ̀ ń pàdé ara wọn,bí wọ́n ti ń sáré lọ sọ fún ọba Babiloni pé ogun ti gba ìlú rẹ̀ patapata.

32. Wọ́n ti gba ibi ìsọdá odò,wọ́n ti dáná sun àwọn ibi ààbò,ìbẹ̀rùbojo sì ti mú àwọn ọmọ ogun.

33. Babiloni dàbí ibi ìpakà, tí a tẹ̀ mọ́lẹ̀ nígbà tí à ń pa ọkà.Láìpẹ́ ọ̀tá yóo dà á wó, yóo sì di àtẹ̀mọ́lẹ̀.Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

34. “Nebukadinesari ọba Babiloni ti run Jerusalẹmu,ó ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,ó ti sọ ọ́ di ohun èlò òfìfo,ó gbé e mì bí erinmi,ó ti kó gbogbo ohun àdídùn inú rẹ̀ jẹ ní àjẹrankùn,ó ti da ìyókù nù.

35. Jẹ́ kí àwọn tí ń gbé Sioni wí pé,‘Kí ibi tí àwọn ará Babiloni ṣe sí wa ati sí àwọn arakunrin wa dà lé wọn lórí.’Kí àwọn ará Jerusalẹmu sì wí pé,‘Ẹ̀jẹ̀ wa ń bẹ lórí àwọn ará ilẹ̀ Kalidea.’ ”

36. Nítorí náà, OLUWA sọ fún àwọn ará Jerusalẹmu pé,“Ẹ wò ó, n óo gba ẹjọ́ yín rò,n óo sì ba yín gbẹ̀san.N óo jẹ́ kí omi òkun Babiloni gbẹ,n óo sì jẹ́ kí orísun odò rẹ̀ gbẹ.

37. Babiloni yóo sì di òkítì àlàpà, ati ibùgbé ajáko,yóo di ibi àríbẹ̀rù ati àrípòṣé, láìsí ẹnìkan kan ninu rẹ̀.

38. Gbogbo wọn yóo bú papọ̀ bíi kinniun,wọn yóo sì ké bí àwọn ọmọ kinniun.

39. Nígbà tí ara wọn bá gbóná,n óo se àsè kan fún wọn.N óo rọ wọ́n lọ́tí yó,títí tí wọn óo fi máa yọ ayọ̀ ẹ̀sín,tí wọn óo sì sùn lọ títí ayé.Wọn óo sùn, wọn kò sì ní jí mọ́.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

40. N óo fà wọ́n lọ sí ibi tí wọn tí ń pa ẹran,bí ọ̀dọ́ aguntan, ati àgbò ati òbúkọ.”

Ka pipe ipin Jeremaya 51