Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 50:20-27 BIBELI MIMỌ (BM)

20. OLUWA ní, Nígbà tí ó bá yá, tí àkókò bá tó, a óo wá ẹ̀ṣẹ̀ tì ní Israẹli ati Juda; nítorí pé n óo dáríjì àwọn tí mo bá ṣẹ́kù.”

21. OLUWA ní,“Ẹ gbógun ti ilẹ̀ Merataimu, ati àwọn ará Pekodi.Ẹ pa wọ́n, kí ẹ sì run wọ́n patapata.Gbogbo nǹkan tí mo pàṣẹ fun yín ni kí ẹ ṣe.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

22. A gbọ́ ariwo ogun ati ìparun ńlá, ní ilẹ̀ náà.

23. Ẹ wo bí a ti gé òòlù tó ti ń lu gbogbo ayé lulẹ̀,tí a sì fọ́ ọ!Ẹ wo bí Babiloni ti di ohun àríbẹ̀rù, láàrin àwọn orílẹ̀-èdè.

24. Mo dẹ tàkúté sílẹ̀ fun yín, ẹ̀yin ará Babiloni:Tàkúté náà mu yín, ẹ kò sì mọ̀.Wọ́n ri yín, ọwọ́ sì tẹ̀ yín,nítorí pé ẹ yájú sí èmi OLUWA.

25. Mo ti ṣí ìlẹ̀kùn ilé ìṣúra àwọn nǹkan ìjà yín,mo sì kó àwọn ohun ìjà ibinu yín jáde,nítorí èmi OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ní iṣẹ́ kan láti ṣe ní ilẹ̀ àwọn ará Kalidea.

26. Ẹ gbógun tì í ní gbogbo ọ̀nà,ẹ ṣí àká rẹ̀ sílẹ̀,ẹ kó o jọ bí òkítì ọkà,kí ẹ sì pa á run patapata,ẹ má dá ohunkohun sí ninu rẹ̀.

27. Ẹ pa gbogbo akọ mààlúù rẹ̀,ẹ fà wọ́n lọ sí ibi tí wọ́n ti ń pa ẹran.Àwọn ará Babiloni gbé, nítorí ọjọ́ wọn ti pé,àní ọjọ́ ìjìyà wọn.”

Ka pipe ipin Jeremaya 50