Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 49:30-36 BIBELI MIMỌ (BM)

30. “Ẹ̀yin ará Hasori, ẹ sá,ẹ lọ jìnnà réré, kí ẹ sì máa gbé inú ọ̀gbun.Nítorí pé Nebukadinesari, ọba Babiloni ń pète ibi si yín,ó ti pinnu ibi si yín.

31. Ó ní, ‘Ẹ dìde kí ẹ gbógun ti orílẹ̀-èdè tí ó wà ní alaafia, ati láìléwu,ìlú tí ó dá dúró tí kò sì ní ìlẹ̀kùn tabi ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn fún ààbò.’

32. “Àwọn ràkúnmí ati agbo ẹran wọn yóo di ìkógun.N óo fọ́n àwọn tí wọn ń gé ẹsẹ̀ irun wọn ká sí igun mẹrẹẹrin ayé,n óo sì mú kí ibi bá wọn láti gbogbo àyíká wọn.

33. Hasori yóo di ibùgbé ajáko,yóo di ahoro títí laelae.Ẹnìkan kò ní gbé ibẹ̀ mọ́,bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò ní dé sibẹ mọ́.”

34. OLUWA àwọn ọmọ ogun bá Jeremaya wolii sọ nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekaya, ọba Juda.

35. Ó ní, “Wò ó! N óo pa àwọn tafàtafà Elamu, tí wọn jẹ́ orísun agbára wọn,

36. n óo mú kí ẹ̀fúùfù mẹrin láti igun mẹrẹẹrin ojú ọ̀run kọlu Elamu; n óo sì fọ́n wọn ká sinu ẹ̀fúùfù náà, kò sì ní sí orílẹ̀-èdè kan tí àwọn ará Elamu kò ní fọ́n ká dé.

Ka pipe ipin Jeremaya 49