Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 49:24-31 BIBELI MIMỌ (BM)

24. Àárẹ̀ mú Damasku,ó pẹ̀yìndà pé kí ó máa sálọ,ṣugbọn ìpayà mú un,ìrora ati ìbànújẹ́ sì dé bá a, bí obinrin tí ń rọbí.

25. Ẹ wò ó bí ìlú olókìkí tí ó kún fún ayọ̀, ṣe di ibi ìkọ̀sílẹ̀!

26. Àwọn ọdọmọkunrin Damasku yóo ṣubú ní gbàgede rẹ̀ ní ọjọ́ náà,gbogbo àwọn ọmọ ogun ibẹ̀ yóo sì parun ni;Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

27. N óo dáná sun odi Damasku,yóo sì jó ibi ààbò Benhadadi.”

28. OLUWA sọ nípa Kedari ati àwọn ìjọba Hasori tí Nebukadinesari ọba Babiloni ṣẹgun pé,“Ẹ dìde kí ẹ gbógun ti Kedari!Ẹ pa àwọn ará ìlà oòrùn run!

29. Ogun yóo kó àgọ́ wọn ati àwọn ẹran ọ̀sìn wọn lọ,ati àwọn aṣọ àgọ́, ati ohun ìní wọn;Ọ̀tá yóo kó ràkúnmí wọn lọ,àwọn eniyan yóo máa kígbe sí wọn pé,‘Ìpayà wà ní gbogbo àyíká.’

30. “Ẹ̀yin ará Hasori, ẹ sá,ẹ lọ jìnnà réré, kí ẹ sì máa gbé inú ọ̀gbun.Nítorí pé Nebukadinesari, ọba Babiloni ń pète ibi si yín,ó ti pinnu ibi si yín.

31. Ó ní, ‘Ẹ dìde kí ẹ gbógun ti orílẹ̀-èdè tí ó wà ní alaafia, ati láìléwu,ìlú tí ó dá dúró tí kò sì ní ìlẹ̀kùn tabi ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn fún ààbò.’

Ka pipe ipin Jeremaya 49