Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 12:3-10 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Ṣugbọn ìwọ OLUWA mọ̀ mí,O rí mi, o sì ti yẹ ọkàn mi wòo mọ èrò mi sí ọ.Fà wọ́n jáde bí aguntan tí wọn ń mú lọ pa,yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ ìparun.

4. Yóo ti pẹ́ tó, tí ilẹ̀ náà yóo máa ṣọ̀fọ̀,tí koríko oko yóo rọ?Nítorí iṣẹ́ burúkú àwọn tí wọn ń gbé inú rẹ̀,àwọn ẹranko ati àwọn ẹyẹ ṣègbé,nítorí àwọn eniyan ń wí pé,“Kò ní rí ohun tí yóo ṣẹlẹ̀ sí wa.”

5. OLUWA ní,“Bí o bá àwọn tí ń fi ẹsẹ̀ sáré sáré, tí ó bá rẹ̀ ọ́,báwo ni o ṣe lè bá ẹṣin sáré?Bí o bá sì ń ṣubú ní ilẹ̀ tí ó tẹ́jú,báwo ni o óo ti ṣe nígbà tí o bá dé aṣálẹ̀ Jọdani?

6. Nítorí pé àwọn arakunrin rẹ pàápàáati àwọn ará ilé baba rẹti hu ìwà ọ̀dàlẹ̀ sí ọ;àwọn gan-an ni wọ́n ń ṣe èké rẹ:Má gbẹ́kẹ̀lé wọn,bí wọ́n bá tilẹ̀ ń sọ̀rọ̀ rere sí ọ.”

7. OLUWA wí pé,“Mo ti kọ ilé mi sílẹ̀;mo ti kọ ogún tí a pín fún mi sílẹ̀.Mo ti fa ẹni tí ọkàn mi ń fẹ́ lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.

8. Ogún mi ti dàbí kinniun inú igbó sí mi,ó ti sọ̀rọ̀ burúkú sí mi;nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.

9. Ṣé ogún mi ti dàbí ẹyẹ igún aláwọ̀ adíkálà ni?Ṣé àwọn ẹyẹ igún ṣùrù bò ó ni?Ẹ lọ pe gbogbo àwọn ẹranko igbó jọ,ẹ kó wọn wá jẹun.

10. Ọpọlọpọ àwọn darandaran ni wọ́n ti ba ọgbà àjàrà mi jẹ́,wọ́n ti tẹ oko mi mọ́lẹ̀,wọ́n sọ oko mi dáradára di aṣálẹ̀.

Ka pipe ipin Jeremaya 12