Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Diutaronomi 33:14-26 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Kí OLUWA pèsè ọpọlọpọ èso sórí ilẹ̀ wọn,kí ó sì kún fún àwọn èso tí ó dára jùlọ láti ìgbà dé ìgbà.

15. Kí àwọn òkè ńláńlá àtijọ́ so ọpọlọpọ èso dáradára,kí ọpọlọpọ èso sì bo àwọn òkè kéékèèké.

16. Kí ilẹ̀ wọn kún fún oríṣìíríṣìí àwọn ohun tí ó dára,pẹlu ibukun láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ń gbé inú pápá tí ń jó.Kí ó wá sórí Josẹfu,àní, sórí ẹni tó jẹ́ aṣiwaju fún àwọn arakunrin rẹ̀.

17. Àkọ́bí rẹ̀ lágbára bí akọ mààlúù,Ìwo rẹ̀ sì dàbí ìwo mààlúù tí ó lágbára,tí yóo fi máa ti àwọn orílẹ̀-èdè títí dé òpin ayé.Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ẹgbẹẹgbaarun àwọn ọmọ Efuraimu,ati ẹgbẹẹgbẹrun àwọn ọmọ Manase.”

18. Ó súre fún Sebuluni ati fún Isakari, ó ní:“Máa yọ̀ bí o ti ń jáde lọ, ìwọ Sebuluni,sì máa yọ̀ ninu ilé rẹ, ìwọ Isakari.

19. Wọn óo pe àwọn àlejò jọ sórí òkè,wọn óo sì máa rú ẹbọ ní ọ̀nà ẹ̀tọ́ níbẹ̀.Nítorí wọn óo máa kó ọrọ̀ jọ láti inú òkun,ati dúkìá tí ó farasin láti inú yanrìn etí òkun.”

20. Ìre tí ó sú fún ẹ̀yà Gadi ni pé:“Ibukun ni fún ẹni tí ó bukun ilẹ̀ Gadi,Gadi dàbí kinniun tí ó ba láti fani lápá ya, ati láti géni lórí.

21. Ibi tí ó dára jùlọ ninu ilẹ̀ náà ni wọ́n mú fún ara wọn,nítorí pé ibẹ̀ ni ìpín olórí ogun wà,ó wá sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí àwọn eniyan náà,àtòun, àtàwọn eniyan náà sì ń pa àṣẹ OLUWA mọ́,wọn sì ń ṣe ìdájọ́ òdodo.”

22. Ó súre fun ẹ̀yà Dani pé:“Dani dàbí ẹgbọ̀rọ̀ kinniun, tí ó fò jáde láti Baṣani.”

23. Ó súre fún ẹ̀yà Nafutali pé:“OLUWA ti ṣíjú rere wo Nafutali,ó sì ti bukun un lọpọlọpọ,ilẹ̀ wọn bẹ̀rẹ̀ láti adágún Galili,títí lọ kan gúsù gbọ̀ngbọ̀n.”

24. Ìre tí ó sú fún ẹ̀yà Aṣeri ni pé:“Ibukun ẹ̀yà Aṣeri ta gbogbo ibukun ẹ̀yà yòókù yọ,àyànfẹ́ ni yóo jẹ́ láàrin àwọn arakunrin rẹ̀,ilẹ̀ rẹ̀ yóo sì kún fún òróró olifi.

25. Ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn rẹ̀ yóo jẹ́ irin ati idẹ,bí iye ọjọ́ orí rẹ̀ bá ti tó, bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóo pọ̀ tó.”

26. Ẹ̀yin ará Jeṣuruni,kò sí ẹni tí ó dàbí Ọlọrun yín,tí ó gun awọsanma lẹ́ṣin ninu ọlá ńlá rẹ̀,láti wá ràn yín lọ́wọ́.

Ka pipe ipin Diutaronomi 33