orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42
  43. 43
  44. 44
  45. 45
  46. 46
  47. 47
  48. 48
  49. 49
  50. 50
  51. 51
  52. 52
  53. 53
  54. 54
  55. 55
  56. 56
  57. 57
  58. 58
  59. 59
  60. 60
  61. 61
  62. 62
  63. 63
  64. 64
  65. 65
  66. 66

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 21 BIBELI MIMỌ (BM)

Ìran nípa Ìṣubú Babiloni

1. Àsọtẹ́lẹ̀ nípa aṣálẹ̀ etí òkun nìyí:àjálù kan ń já bọ̀ láti inú aṣálẹ̀,láti ilẹ̀ tí ó bani lẹ́rù,ó ń bọ̀ bí ìjì líle tí ń jà bọ̀ láti ìhà àríwá aṣálẹ̀.

2. Ìran tí a fi hàn mí yìí le:Àwọn oníjàgídíjàgan lọ digun kó ìkógun,abanǹkanjẹ́ sì ba nǹkan jẹ́.Ẹ̀yin ará Elamu, ẹ gòkè lọ!Ẹ̀yin ará Media, ẹ múra ogun!Mo ti fòpin sí òṣé ati ìjìyà tí Babiloni kó bá gbogbo eniyan.

3. Nítorí náà, gbogbo ẹ̀gbẹ́ ní ń dùn mí,gbogbo ara ní ń ro míbí obinrin tí ń rọbí lọ́wọ́.A tẹrí mi ba kí n má baà gbọ́ nǹkankan,wọ́n dẹ́rù bà mí kí n má baà ríran.

4. Ọkàn mi dààmú, jìnnìjìnnì dà bò mí;wọ́n ti sọ àfẹ̀mọ́júmọ́ tí mò ń retí di ìbẹ̀rù mọ́ mi lọ́wọ́.

5. Wọ́n tẹ́ tabili, wọ́n sì tẹ́ aṣọ sílẹ̀wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu.Ariwo bá ta pé“Ẹ gbéra nílẹ̀, ẹ̀yin ológun!Ẹ fepo pa asà yín.”

6. Nítorí OLUWA wí fún mi pé:“Lọ fi aṣọ́nà ṣọ́ ojú ọ̀nà,kí ó máa kéde ohun tí ó bá rí.

7. Nígbà tí ó bá rí àwọn ẹlẹ́ṣintí wọn ń bọ̀ ní meji-meji, bí ó bá rí ití àwọn kan gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,tí àwọn kan gun ràkúnmí,kí ó fara balẹ̀ dáradára,kí ó dẹtísílẹ̀ dáradára.”

8. Ẹni tí ń ṣọ́nà kígbe pé:“OLUWA mi, lórí ilé-ìṣọ́ ni èmi í dúró sí lojoojumọ,níbi tí a fi mí ṣọ́, ni èmi í sì í wà ní òròòru.

9. Ẹ wò ó! Àwọn ẹlẹ́ṣin kan ń bọ̀,wọ́n fẹ̀gbẹ́kẹ̀gbẹ́ ní meji-meji!”“Ẹ gbọ́! Ìlú Babiloni ti wó! Ó ti wó!Pẹlu gbogbo àwọn oriṣa rẹ̀,ó ti wó lulẹ̀ patapata.”

10. Ẹ̀yin eniyan mi tí a ti tẹ̀ mọ́lẹ̀,bí ẹni tẹ ọkà ní ibi ìpakà,ohun tí mo gbọ́ láti ọ̀dọ̀ OLUWA àwọn ọmọ ogun,Ọlọrun Israẹli, ní mò ń kéde fun yín yìí.

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Edomu

11. Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Edomu nìyí:Ẹnìkan ń pè mí láti SeiriÓ ní: “Aṣọ́nà, Òru ti rí o?Aṣọ́nà, àní òru ti rí?”

12. Aṣọ́nà bá dáhùn, ó ní:“Ilẹ̀ ń ṣú, ilẹ̀ sì ń mọ́.Bí ẹ bá tún fẹ́ bèèrè,ẹ pada wá, kí ẹ tún wá bèèrè.”

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Arabia

13. Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Arabia nìyí:Ninu igbó Arabia ni ẹ óo sùn, ẹ̀yin èrò ará Didani.

14. Ẹ bu omi wá fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ.Ẹ gbé oúnjẹ pàdé ẹni tí ń sá fógun, ẹ̀yin ará ilẹ̀ Tema.

15. Wọ́n ń sá fún idà,wọ́n sá fún idà lójú ogun.Wọ́n ń sá fún àwọn tafàtafà,wọ́n sá fún líle ogun.

16. OLUWA sọ fún mi pé, “Kí ó tó tó ọdún kan, ní ìwọ̀n ọdún alágbàṣe kan, gbogbo ògo Kedari yóo dópin;

17. díẹ̀ ni yóo sì kù ninu àwọn tafàtafà alágbára ọmọ Kedari; nítorí OLUWA Ọlọrun Israẹli ló sọ bẹ́ẹ̀.”