orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3
  4. 4
  5. 5
  6. 6
  7. 7
  8. 8
  9. 9
  10. 10
  11. 11
  12. 12
  13. 13
  14. 14
  15. 15
  16. 16
  17. 17
  18. 18
  19. 19
  20. 20
  21. 21
  22. 22
  23. 23
  24. 24
  25. 25
  26. 26
  27. 27
  28. 28
  29. 29
  30. 30
  31. 31
  32. 32
  33. 33
  34. 34
  35. 35
  36. 36
  37. 37
  38. 38
  39. 39
  40. 40
  41. 41
  42. 42
  43. 43
  44. 44
  45. 45
  46. 46
  47. 47
  48. 48
  49. 49
  50. 50
  51. 51
  52. 52
  53. 53
  54. 54
  55. 55
  56. 56
  57. 57
  58. 58
  59. 59
  60. 60
  61. 61
  62. 62
  63. 63
  64. 64
  65. 65
  66. 66

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 57 BIBELI MIMỌ (BM)

OLUWA Dá Ìwà Ìbọ̀rìṣà Israẹli lẹ́bi

1. Olódodo ń ṣègbé,kò sí ẹni tí ó fi ọkàn sí i.A mú àwọn olótìítọ́ kúrò, kò sì sí ẹni tí ó yé,pé à ń yọ olódodo kúrò ninu ìdààmú ni.

2. Àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà òtítọ́, wọn óo wà ní alaafia,wọn óo máa sinmi lórí ibùsùn wọn.

3. Ẹ̀yin ọmọ oṣó wọnyi,ẹ súnmọ́bí fún ìdájọ́,ẹ̀yin ọmọ alágbèrè ati panṣaga.

4. Ta ni ẹ̀ ń fi ṣe ẹlẹ́yà?Ta ni ẹ̀ ń ya ẹnu ní ìyàkuyà sítí ẹ yọ ṣùtì sí?Ṣebí ọmọ ẹ̀ṣẹ̀ ni yínirú ọmọ ẹ̀tàn;

5. ẹ̀yin tí ẹ kún fún ìṣekúṣe lábẹ́ igi Oaku,ati lábẹ́ gbogbo igi eléwé tútù.Ẹ̀yin tí ẹ̀ ń pa àwọn ọmọ yín láàrin àfonífojì,ati ní abẹ́ àpáta?

6. Àwọn oriṣa láàrin àwọn òkúta ọ̀bọ̀rọ́, ninu àfonífojì,àwọn ni ẹ̀ ń sìn,àwọn ni ò ń da ẹbọ ohun mímu lé lórí,àwọn ni ò ń fi nǹkan jíjẹ rúbọ sí.Ṣé àwọn nǹkan wọnyi ni yóo mú kí inú mi yọ́?

7. Lórí òkè gíga fíofío, ni o lọ tẹ́ ibùsùn rẹ síníbẹ̀ ni o tí ń lọ rú ẹbọ.

8. O gbé ère oriṣa kalẹ̀ sí ẹ̀yìn ìlẹ̀kùn ati ẹ̀yìn òpó ìlẹ̀kùn.O kọ̀ mí sílẹ̀, o bọ́ sórí ibùsùn, o tẹ́ ibùsùn tí ó fẹ̀.O wá bá àwọn tí ó wù ọ́ da ọ̀rọ̀ pọ̀,ẹ̀ ń bá ara yín lòpọ̀.

9. O gbọ̀nà, o lọ gbé òróró fún oriṣa Moleki,o kó ọpọlọpọ turari lọ,o rán àwọn ikọ̀ lọ sí ilẹ̀ òkèèrè,o sì ranṣẹ lọ sinu isà òkú pẹlu.

10. Àárẹ̀ mú ọ nítorí ìrìn àjò rẹ jìnnà,sibẹsibẹ o kò sọ fún ara rẹ pé, “Asán ni ìrìn àjò yìí.”Ò ń wá agbára kún agbára,nítorí náà àárẹ̀ kò mú ọ.

11. Ta ni ń já ọ láyà,tí ẹ̀rù rẹ̀ bà ọ́, tí o fi purọ́;tí o kò ranti mi, tí o kò sì ronú nípa mi?Ṣé nítorí mo ti dákẹ́ fún ìgbà pípẹ́,ni o kò fi bẹ̀rù mi?

12. N óo sọ nípa òdodo rẹ ati iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,ṣugbọn wọn kò ní lè ràn ọ́ lọ́wọ́.

13. Nígbà tí o bá kígbe,kí àwọn ère tí o kó jọ gbà ọ́.Atẹ́gùn lásán ni yóo gbé gbogbo wọn lọAfẹ́fẹ́ ni yóo fẹ́ wọn lọ.Ṣugbọn ẹni tí ó bá sá di mí,ni yóo ni ilẹ̀ náà,òun ni yóo sì jogún òkè mímọ́ mi.

Ọlọrun Ṣe Ìlérí Ìrànlọ́wọ́ ati Ìwòsàn

14. OLUWA ní, “Ẹ la ọ̀nà, ẹ la ọ̀nà, ẹ tún ọ̀nà ṣe,ẹ mú gbogbo ohun ìkọsẹ̀ kúrò lọ́nà àwọn eniyan mi.”

15. Nítorí Ẹni Gíga, tí ó ga jùlọ,ẹni tí ń gbé ninu ayérayé, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mímọ́:òun ni ó ní, “Ibi gíga ati mímọ́ ni mò ń gbé lóòótọ́,ṣugbọn mo wà pẹlu àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn ati àwọn onírẹ̀lẹ̀.Láti sọ ọkàn wọn jí.

16. Nítorí n kò ní máa jà títí ayé,tabi kí n máa bínú nígbà gbogbo:nítorí láti ọ̀dọ̀ mi ni ẹ̀mí ti ń jáde,Èmi ni mo dá èémí ìyè.

17. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ojúkòkòrò rẹ̀, inú bí mi,mo jẹ ẹ́ níyà, mo fojú pamọ́, inú sì bí mi;sibẹ ó túbọ̀ ń ṣìnà sí i ni, ó ń ṣe tinú rẹ̀.

18. Mo ti rí bí ó ti ń ṣe,ṣugbọn n óo ṣì wò ó sàn;n óo máa darí rẹ̀, n óo tù ú ninu,n óo sì fún àwọn tí ó bá ń ṣọ̀fọ̀ ní Israẹli ní orin ayọ̀.

19. Alaafia ni, alaafia ni fún àwọn tí ó wà ní òkèèrè,ati àwọn tí ó wà nítòsí;n óo sì wò wọ́n sàn.

20. Ṣugbọn àwọn eniyan burúkú dàbí ríru omi òkun,nítorí òkun kò lè sinmi,omi rẹ̀ a sì máa rú pàǹtí ati ẹrẹ̀ sókè.

21. Kò sí alaafia fún àwọn eniyan burúkú.”Ọlọrun mi ló sọ bẹ́ẹ̀.