Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 14:57-64 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

57. Níkẹyìn àwọn kan dìde, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ́rìí èké sí i, wọ́n ní

58. “A gbọ́ tí ó wí pé ‘Èmi yóò wó tẹ́ḿpìlì tí ẹ fi ọwọ́ kọ́ yìí, nígbà tí yóò bá sì fi di ọjọ́ kẹta, èmi yóò kọ́ òmíràn ti a kò fi ọwọ́ ènìyàn kọ́.’ ”

59. Ṣíbẹ̀, ẹ̀rí i wọn kò dọ́gba

60. Nígbà náà ni àlùfáà àgbà dìde, ó bọ́ ṣíwájú. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í bi Jésù léèrè, ó ní, “Ṣé o kò ní fèsì sí ẹ̀sùn tí wọ́n fi sùn ọ? Kí ni ìwọ gan an ní sọ fúnrarẹ?”

61. Ṣùgbọ́n Jésù dákẹ́.Olórí àlùfáà tún bi í, lẹ́ẹ̀kan sí i, ò ní, “Ṣé ìwọ ni Kírísítì náà, Ọmọ Ọlọ́run?”

62. Jésù wá dáhùn, ó ni, “Èmi ni: Ẹ̀yin yóò sì rí Ọmọ-Ènìyàn tí yóò jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún agbára. Ẹ̀yin yóò sì tún rí Ọmọ-Ènìyàn tí ó ń bọ̀ láti inú àwọ̀sánmọ̀ ojú ọ̀run.”

63. Nígbà náà ni Olórí àlùfáà fa aṣọ rẹ̀ ya, ó ní, “Kí ló kù tì a ń wá? Kí ni a tún ń wá ẹlẹ́rí fún?

64. Ẹ̀yin fúnra yín ti gbọ́ ọ̀rọ̀ òdì tí ó sọ. Kí ni ẹ rò pé ó tọ́ kí a ṣe?”Gbogbo wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ó jẹ̀bi ìkú.”

Ka pipe ipin Máàkù 14