Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 13:10-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Nítorí pé ẹ gbọdọ̀ kọ́kọ́ wàásù ìyìnrere náà fún gbogbo orílẹ̀ èdè kí òpin tó dé.

11. Ṣùgbọ́n nígbà tí a bá mú yín, tí ẹ sì dúró níwájú adájọ́, ẹ má ṣe dààmú nípa ohun tí ẹ ó wí fún ààbò. Ẹ ṣáà sọ ohun tí Ọlọ́run bá fi sí yín lọ́kàn. Ẹ̀yin kọ́ ní yóò sọ̀rọ̀, bí kò ṣe Ẹ̀mí Mímọ́.

12. “Arákùnrin yóò máa fi ẹ̀sùn kan arákùnrin rẹ̀, tí yóò sì yọrí sí ikú. Baba yóò máa ṣe ikú pa ọmọ rẹ̀. Àwọn ọmọ yóò máa dìtẹ̀ sí òbí wọn. Àní, àwọn ọmọ pẹ̀lú yóò máa ṣekú pa òbí wọn.

13. Àwọn ènìyàn yóò kórira yín nítorí tí ẹ jẹ́ tèmi. Ṣùgbọ́n ẹni tó bá fara da ìyà títí dé òpin tí kò sì kọ̀ mí sílẹ̀ òun ni yóò rí ìgbàlà.

14. “Ṣùgbọ́n nígba tí ẹ̀yin bá rí ìríra ìsọdahoro, tí ó dúró ní bí tí kò tọ́, tí a tí ẹnu wòlíì Dáníẹ́lì sọ, (ẹnikẹ́ni tí ó bá kà á ki í ó yé e) nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ni Jùdíà sá lọ sí orí òkè.

15. Kí ẹni ti ń bẹ lórí ilé má ṣe sọkalẹ̀ lọ sínú ilé, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má si ṣe wọ inú rẹ̀, láti mú ohunkóhun jáde nínú ilé rẹ̀.

16. Kí ẹni tí ó wà lóko má ṣe padà ṣẹ́yìn láti wá mú aṣọ rẹ̀.

17. ègbé ní fún àwọn tí ó lóyún, àti fún obìnrin tí ń fún fọ́mọ lọ́mú ní ọjọ́ wọ̀nyí.

18. Kí ẹ sì máa gbàdúrà pé kí ìsákúrò nínú ewu yìí má ṣẹlẹ̀ ní àkókò òtútù.

19. Nítorí ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì yóò jẹ́ àkókò ìpọ́njú, irú èyí tí kò ì ṣẹlẹ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀dá Ọlọ́run. Irú rẹ̀ kò sì ni ṣẹlẹ̀ mọ́.

20. À fi tí Olúwa bá gé àkókò ìjìyà náà kúrú, ẹyọ ẹ̀mí kan ní ayé kì yóò là. Ṣùgbọ́n nítorí àwọn tí Ọlọ́run yàn, ni yóò ṣe dín àwọn ọjọ́ náà kù.

Ka pipe ipin Máàkù 13