Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 6:8-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ṣùgbọ́n ó mọ ìrò inú wọn, ó sì wí fún ọkùnrin náà tí ọwọ́ rẹ̀ rọ pé, “Dìde, kí o sì dúró láàrin.” Ó sì dìde dúró.

9. Nígbà náà ni Jésù wí fún wọn pé, “Èmi bi yín léèrè, Ó ha tọ́ láti máa ṣe rere ni ọjọ́ ìsinmi, tàbí láti máa ṣe búburú? Láti gba ọkàn là, tàbí láti pa á run?”

10. Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká, ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀: ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ̀ sípò gẹ́gẹ́ bí èkejì.

11. Wọ́n sì kún fún ìbínú gbígbóná; wọ́n sì bá ara wọn rò ohun tí àwọn ìbá ṣe sí Jésù.

12. Ọ̀kan nínú àwọn ọjọ́ wọnnì, Jésù lọ sí orí òkè lọ gbàdúrà, ó sì fi gbogbo òru náà gbàdúrà sí Ọlọ́run.

13. Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; nínú wọn ni ó sì yan méjìlá, tí ó sì sọ ní àpósítélì.

14. Símónì (ẹni tí a pè ní Pétérù) àti Ańdérù arákùnrin rẹ̀, Jákọ́bù àti Jòhánù, Fílípì àti Batolóméù.

15. Mátíù àti Tọ́másì, Jákọ́bù ọmọ Álíféù, àti Símónì tí a ń pè ní Ṣélótè,

16. Àti Júdà arákùnrin Jákọ́bù, àti Júdásì Ísíkáríótù tí ó di ọ̀dàlẹ̀.

17. Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀, ó sì dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú ọpọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn, láti gbogbo Jùdéà, àti Jerúsálémù, àti agbègbè Tírè àti Ṣídónì, tí wọ́n wá láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìmúláradá kúrò nínú àrùn wọn;

18. Àti àwọn tí ara wọn kún fún ẹ̀mí àìmọ́; ni ó sì mú láradá.

19. Gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń fẹ́ láti fọwọ́ kàn án, nítorí tí àṣẹ ń jáde lára rẹ̀, ó sì mú gbogbo wọn láradá.

20. Nígbà tí ó sì gbé ojú rẹ̀ sókè sí àwọn ọmọ èyìn rẹ̀, ó ní:“Alábùkún fún ni ẹ̀yin òtòsì,nítorí tiyín ni ìjọba Ọlọ́run.

21. Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ebi ń panísinsin yìí; nítorí tí ẹ ó yòó.Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ńsọkún nísinsin yìí: nítorí tí ẹ̀yin ó rẹ́rìn-ín.

22. Alábùkún fún ni ẹ̀yin, nígbà tí àwọn ènìyàn bá kóríra yín,tí wọ́n bá yà yín kúrò nínú ẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n bá gàn yín,tí wọ́n bá ta orúkọ yín nù bí ohun búburú, nítorí ọmọ ènìyàn.

23. “Kí ẹ̀yin yọ̀ ní ọjọ́ náà, kí ẹ̀yin sì fò sókè fún ayọ̀, nítorí tí ẹ̀yin ti gba ìtùnú yín ná.

Ka pipe ipin Lúùkù 6