Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 6:15-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Mátíù àti Tọ́másì, Jákọ́bù ọmọ Álíféù, àti Símónì tí a ń pè ní Ṣélótè,

16. Àti Júdà arákùnrin Jákọ́bù, àti Júdásì Ísíkáríótù tí ó di ọ̀dàlẹ̀.

17. Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀, ó sì dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú ọpọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn, láti gbogbo Jùdéà, àti Jerúsálémù, àti agbègbè Tírè àti Ṣídónì, tí wọ́n wá láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìmúláradá kúrò nínú àrùn wọn;

18. Àti àwọn tí ara wọn kún fún ẹ̀mí àìmọ́; ni ó sì mú láradá.

19. Gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń fẹ́ láti fọwọ́ kàn án, nítorí tí àṣẹ ń jáde lára rẹ̀, ó sì mú gbogbo wọn láradá.

20. Nígbà tí ó sì gbé ojú rẹ̀ sókè sí àwọn ọmọ èyìn rẹ̀, ó ní:“Alábùkún fún ni ẹ̀yin òtòsì,nítorí tiyín ni ìjọba Ọlọ́run.

21. Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ebi ń panísinsin yìí; nítorí tí ẹ ó yòó.Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ńsọkún nísinsin yìí: nítorí tí ẹ̀yin ó rẹ́rìn-ín.

Ka pipe ipin Lúùkù 6