Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 3:8-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ sí bi tí ó gbé wù ú, ìwọ sì ń gbọ́ ìró rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ kò mọ ibi tí ó gbé ti wá, àti ibi tí ó gbé ń lọ: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa ti Ẹ̀mí.”

9. Nikodémù dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Nǹkan wọ̀nyí yóò ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀?”

10. Jésù dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ṣé olùkọ́ni ní Ísírẹ́lì ni ìwọ ń ṣe, o kò sì mọ nǹkan wọ̀nyí?

11. Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Àwa ń sọ èyí tí àwa mọ̀, a sì ń jẹ́rìí èyí tí àwa ti rí; ẹ̀yin kò sì gba ẹ̀rí wa.

12. Bí mo bá sọ ohun ti ayé yìí fún yín, tí ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbàgbọ́ bí mo bá sọ ohun ti ọ̀run fún yín?

13. Kò sì sí ẹni tí ó gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, Ọmọ Ènìyàn tí ń bẹ ní ọ̀run.

14. Bí Móse sì ti gbé ejò sókè ní ihà, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni a kò le ṣe aláìgbé Ọmọ-Ènìyàn sókè pẹ̀lú:

15. Kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, kí ó má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó le ní iyè àìnípẹ̀kun.

16. “Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, tí ó fi ọmọ bíbí rẹ̀ kan ṣoṣo fúnni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní iyè àìnípẹ̀kun.

17. Nítorí Ọlọ́run kò rán ọmọ rẹ̀ sí ayé láti dá aráyé lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n kí a le ti ipaṣẹ̀ rẹ̀ gba aráyé là.

18. Ẹni tí ó bá gbà á gbọ́, a kò ní dá a lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n a ti dá ẹni tí kò gbà á gbọ́ lẹ́jọ́ ná, nítorí tí kò gba orúkọ ọmọ bíbí kan ṣoṣo ti Ọlọ́run gbọ́.

19. Èyí ni ìdájọ́ náà pé, ìmọ́lẹ̀ wá sí ayé, àwọn ènìyàn sì fẹ́ òkùnkùn ju ìmọ́lẹ̀ lọ, nítorí tí iṣẹ́ wọn burú.

20. Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ó bá hùwà búburú níí ìkórìíra ìmọ́lẹ̀, kìí sí wá sí ìmọ́lẹ̀, kí a má ṣe bá iṣẹ́ rẹ̀ wí.

21. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ níí wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”

22. Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jésù pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Jùdíà; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.

23. Jòhánù pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Áhínónì, ní agbégbé Sálímù, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀: wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọmi.

24. Nítorí tí a kò tí ì sọ Jòhánù sínú túbú.

25. Nígbà náà ni iyàn kan wà láàárin àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Jòhánù, àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.

26. Wọ́n sì tọ Jòhánù wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rábì, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jọ́dánì, tí ìwọ ti jẹ́rí rẹ̀, wò ó, òun tẹ ni bọmi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”

27. Jòhánù dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí ǹkankan gbà, bí kò ṣepé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.

28. Èyin fúnra yín jẹ́rìí mi, pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kírísítì náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi ṣíwájú rẹ̀.’

Ka pipe ipin Jòhánù 3