Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 21:19-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. (Ó wí èyí, ó fi ń ṣàpẹrẹ irú ikú tí yóò fi yin Ọlọ́run lógo.) Lẹ́yìn ìgbà tí ó sì ti wí èyí tan, ó wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”

20. Pétérù sì yípadà, ó rí ọmọ-ẹ̀yìn náà, ẹni tí Jésù fẹ́ràn, ń bọ̀ lẹ́yìn; ẹni tí ó fararọ̀ súnmọ́ àyà rẹ̀ nígbà oúnjẹ alẹ́ tí ó sì wí fún un pé, “Olúwa, ta ni ẹ̀ni tí ó fi ọ́ hàn?”

21. Nígbà tí Pétérù rí i, ó wí fún Jésù pé, “Olúwa, Eléyìí ha ńkọ́?”

22. Jésù wí fún un pé, “Bí èmi bá fẹ́ kí ó dúró títí èmi ó fi dé, kínni èyí jẹ́ sí ọ? Ìwọ máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”

Ka pipe ipin Jòhánù 21