Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 5:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ìwọ sì tí ṣe wọ́n ni ọba àti àlùfáà sì Ọlọ́run wá:wọ́n sì ń jọba lórí ilẹ̀ ayé.”

11. Èmi sì wò, mo sì gbọ́ ohùn àwọn ańgẹ́lì púpọ̀ yí ìtẹ́ náà ká, àti yí àwọn ẹ̀dá alààyè náà àti àwọn àgbà náà ká: Iye wọn sì jẹ́ ẹgbàárun ọ̀nà ẹgbàarún àti ẹgbẹẹgbẹ̀rún ọ̀nà ẹgbẹẹgbẹ̀rún.

12. Wọn ń wí lóhùn rara pé:“Yíyẹ ni Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà tí a tí pa,láti gba agbára,àti ọ̀rọ̀ àti ọgbọ́n, àti ipá, àti ọlá,àti ògo, àti ìbùkún.”

13. Gbogbo ẹ̀dá tí o sì ń bẹ ni ọ̀run, àti lórí ilẹ̀ ayé, àti nísàlẹ̀ ilẹ̀ àti irú àwọn tí ń bẹ nínú òkun, àti gbogbo àwọn tí ń bẹ nínú wọn, ni mo gbọ́ tí ń wí pé,“Kí a fi ìbùkún àti ọlá, àti ògo, àti agbára,fún Ẹni tí ó jókòó lórí ìtẹ́ àti fún Ọ̀dọ́-Àgùntànnáà láé àti láéláé.”

14. Àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà wí pé, “Àmín!” Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà wólẹ̀, wọn sì foríbalẹ̀ fún ẹni tí ń bẹ láàyè láé àti láéláé.

Ka pipe ipin Ìfihàn 5