Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 2:7-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mi ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá ṣẹ́gun ni èmi yóò fi èso igi ìye nì fún jẹ, tí ń bẹ láàrin Párádísè Ọlọ́run.

8. “Àti sí Ańgẹ́lì Ìjọ ní Símírínà Kọ̀wé:Nǹkan wọ̀nyí ni ẹni tí í ṣe ẹni-ìṣáájú àti ẹni-ìkẹyìn wí, ẹni tí ó ti kú, tí ó sì tún yè:

9. Èmi mọ iṣẹ́ rẹ, àti ìpọ́njú, àti àìní rẹ—ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ ni ọ́ èmi sì mọ ọ̀rọ̀-òdì tí àwọn tí ń wí pé Júù ni àwọn tìkárawọn, tí wọn kì sì í ṣe bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n tí wọ́n jẹ́ sínágọ́gù ti Sátánì.

10. Máṣe bẹ̀rù ohunkóhun tí ìwọ ń bọ wá jìyà rẹ̀. Kíyèsí i, èṣù yóò gbé nínú yín jù sínú túúbú, kí a lè dán yin wò; ẹ̀yin ó sì ní ìpọ́njú ní ọjọ́ mẹ́wàá: ìwọ sa se olóòtọ́ dé ojú ikú, èmi ó sì fi adé ìyè fún ọ

11. Ẹni tí ó bá ní etí kí ó gbọ́ ohun tí Ẹ̀mí ń sọ fún àwọn ìjọ. Ẹni tí ó bá sẹ́gun kì yóò farapa nínú ikú kejì.

12. “Àti sì Ańgẹ́lì ìjọ ni Págámọ́sì Kọ̀wé:Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni ẹni tí ó ní ídà mímú olójú méjì,

Ka pipe ipin Ìfihàn 2