Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 8:22-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Nítorí náà ronúpìwàdà ìwà búrurú rẹ yìí, kí ó sì gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run bóyá yóò dári ète ọkàn rẹ jì ọ́.

23. Nítorí tí mo wòye pé, ìwọ wa nínú òróǹrò ìkorò, àti ní ìdè ẹ̀ṣẹ̀.”

24. Nígbà náà ni Símónì dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ gbàdúrà sọ́dọ̀ Olúwa fún mi, kí ọ̀kan nínú ohun tí ẹ̀yin tí sọ má ṣe bá mi.”

25. Nígbà tí wọn sì ti jẹ́rìí, ti wọn ti sọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Pétérù àti Jòhánù padà lọ sí Jerúsálémù, wọ́n sì wàásù ìyìn rere ni ìletò púpọ̀ ti àwọn Samaríà.

26. Ańgẹ́lì Olúwa sì sọ fún Fílípì pé, “Dìde kí ó sì máa lọ sí ìhà gúsù, sí ọ̀nà ijù, tí ó ti Jerúsálémù lọ sí Gásà.”

27. Nígbà tí ó sì dìde, ó lọ; sí kíyèsí, ọkùnrin kan ará Etiópíà, ìwẹ̀fà ọlọ́lá púpọ̀ lọdọ̀ Káńdákè ọba-bìnrin àwọn ara Etiópíà, ẹni tí í se olórí ìsúra rẹ̀, tí ó sì ti wá sí Jerúsálémù láti jọ́sìn,

28. Òun sì ń padà lọ, ó sì jókòó nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó ń ka ìwé wòlíì Àìṣáyà.

29. Ẹ̀mí sì wí fún Fílípì pé, “Lọ kí ó si da ara rẹ pọ̀ mọ́ kẹ̀kẹ́ yìí.”

30. Fílípì si súré lọ, ó gbọ́ ti ó ń ka ìwé wòlíì Àìṣáyà, Fílípì sì bí i pé, “Ohun tí ìwọ ń kà yìí ha yé ọ bí?”

31. Ó sì dáhùn wí pé, “Yóò ha ṣe yé mi, bí kò ṣe pé ẹnìkan tọ́ mí sí ọ̀nà?” Ó sì bẹ Fílípì kí ó gòkè wá, kí ó sì bá òun jókòó.

32. Ibi-ìwé-mímọ́ tí Ìwẹ̀fà náà ń kà náà ni èyí:“A fà á bí àgùntàn lọ fún pípa;àti bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí ń dákẹ́ níwájú olúrẹ́run rẹ̀,bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni kò wí ohun kan.

33. Nínú ìwà ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ a fi ìdájọ́-ododo dùn ún:Ta ni ó le sọ̀rọ̀ nípa ti àwọn ìran rẹ̀?Nítorí tí a gba ẹ̀mí rẹ̀ kúrò ní ayé.”

34. Ìwẹ̀fà náà sì sọ fún Fílípì pé, “Mo bẹ̀ ọ́ sọ fún mi, nípa ta ni wòlíì náà ń sọ ọ̀rọ̀ yìí, nípa ara rẹ̀ tàbí nípa ẹlòmìíràn?”

35. Fílípì sí ya ẹnu rẹ̀, ó sì bẹ̀rẹ̀ láti ibi ìwé-mímọ́ yìí, ó sí wàásù ìyìn rere ti Jésù fún un.

36. Bí wọ́n sì tí ń lọ lọ́nà, wọ́n dé ibi omi kan; ìwẹ̀fà náà sì wí pé, “Wò ó, omi nìyí. Kín ni ó dá mi dúró láti bamitíìsì?”

37. Fílípì sì wí pé, “Bí ìwọ bá gbàgbọ́ tọkàntọkàn, a lè bamitíìsì rẹ.” Ìwẹ̀fà náà sì dáhùn pé, “Mo gbàgbọ́ pé Jésù Kírísítì Ọmọ Ọlọ́run ni.”

38. Ó sì pàṣẹ kí kẹ̀kẹ́ dúró jẹ́; àwọn méjèèjì Fílípì àti Ìwẹ̀fà sì sọ̀kalẹ̀ lọ sínú omi, Fílípì sì bamitíìsì rẹ̀.

39. Nígbà tí wọ́n sí jáde kúrò nínú omi Ẹ̀mí Olúwa gbé Fílípì lọ, ìwẹ̀fà kò sì rí i mọ́; nítorí tí ó ń bá ọ̀nà rẹ̀ lọ, ó ń yọ̀.

40. Fílípì sì bá ara rẹ̀ ní ìlú Ásótù, bí ó ti ń kọ́ja lọ, o wàásù ìyìn rere ní gbogbo ìlú, títí ó fi dé Kesaríà.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 8