Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7:27-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. “Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fínràn sí ẹnìkejì rẹ̀ tì Mósè sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó wí pé, ‘Ta ni ó fi ọ jẹ olórí àti onídàjọ́ wa?

28. Àbí ìwọ ń fẹ́ pa mi gẹ́gẹ́ bí o ti pa ará Íjíbítì lánàá?’

29. Mósè sì sá nítorí ọ̀rọ̀ yìí, ó sì wa ṣe àtìpó ni ilẹ̀ Mídíànì, níbi tí ó gbé bí ọmọ méjì.

30. “Nígbà tí ogójì ọdún sì pé, ańgẹ́lì Olúwa fara hàn Mósè ní ijù, ní òkè Sínáì, nínú ọ̀wọ́ iná ìgbẹ́.

31. Nígbà tí Mósè sì rí i, ẹnu yà á sí ìran náà; nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti wò ó fín, ohùn Olúwa kọ sí i,

32. Wí pé ‘Èmi ni Ọlọ́run àwọn baba rẹ, Ọlọ́run Ábúráhámù àti Ọlọ́run Ísáákì, àti Ọlọ́run Jákọ́bù,’ Mósè sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù, kò sì dàṣà láti wò ó mọ́.

33. “Olúwa sì wí fún un pé, ‘Tú bátà rẹ kúrò ni ẹsẹ̀ rẹ, nitorí ibi tí ìwọ gbé dúró sí yìí ilẹ̀ mímọ́ ni.

34. Ní rírí mo ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi tí ń bẹ ni Íjíbítì, mo sì ti gbọ́ ìkérora wọn, mo sì sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n. Wá nísinsìn yìí, èmi ó sì rán ọ lọ sí ilẹ̀ Íjíbítì.’

35. “Mósè náà yìí tí wọ́n kọ̀, wí pé, ‘Ta ni ó fi jẹ olórí àti onídàájọ́?’ Òun náà ni Ọlọ́run rán lọ láti ọwọ́ ańgẹ́lì, tí ó farahàn án ní ìgbẹ́, láti ṣe olórí àti olùdáǹdè.

36. Òun ni ó mú wọn jáde, lẹ́yìn ìgbà tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì ní ilẹ̀ Íjíbítì, àti ni òkun pupa, àti ni ihà ní ogójì ọdún.

37. “Èyí ni Mósè náà ti ó wí fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, ‘Ọlọ́run yóò gbé wòlíì kan bí èmi dìde nínú àwọn ènìyàn yín.’

38. Èyí náà ni ẹni tí ó wà nínú ìjọ ní ijù pẹ̀lú ańgẹ́lì náà tí ó bá a sọ̀rọ̀ ní orí òkè Sínáì, àti pẹ̀lú àwọn baba wa; ẹni ti ó gba ọ̀rọ̀ ìyè láti fi fún wa.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7