Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà ni olorí àlùfáà wí pé, “Òtítọ́ ha ni àwọn ẹ̀sùn tí wọ́ fi kàn ọ́ bí?”

2. Ní ìdáhùn sí èyí ó wí pé, “Ẹ̀yin arakùnrin àti ẹ̀yin baba, ẹ fetísílẹ̀ sí mi! Ọlọ́run ògo fi ara hàn fún Ábúráhámù baba wa, nígbà tí ó wà ni Mesopotamíà, kí ó to ṣe àtìpó ni Háránì.

3. Ọlọ́run fún un pé, ‘Jáde kúrò ni orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ìbátan rẹ, kí ó sì lọ sí ilẹ̀ tí èmi yóò fi hàn ọ́.’

4. “Nígbà náà ni ó jáde kúrò ní ilẹ̀ àwọn ará Kálídíà, ó sì ṣe àtipó ni Háránì. Lẹ́yìn ìgbà tí baba rẹ̀ sì kú, Ọlọ́run mú un sípò padà wá sí ilẹ̀ yìí, níbi tí ẹ̀yin ń gbé báyìí.

5. Kò sí fún un ni ìní kan, àní tó bi ìwọ̀n ààyè ẹṣẹ̀ kan. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run se ìlérí fún pé, òun yóò fi ilẹ̀-ìní náà fún un àti fún àwọn irú ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí kò tí ì ní ọmọ.

6. Ọlọ́run sì sọ báyìí pé: ‘Irú-ọmọ rẹ̀ yóò ṣe àtìpó ni ilẹ̀ àjèjì; wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú ni irínwó ọdún.’

7. Ọlọ́run wí pé, ‘Orílẹ̀-èdè náà tí wọn ó ṣe ẹrú fún ni èmi ó dá lẹ́jọ́; lẹ́yìn náà ni wọn ó sì wá sìn mí níhín yìí.’

8. Ó sì fún Ábúráhámù ni májẹ̀mú ìkọlà. Ábúráhámù bí Ísáákì, ó kọ ọ́ ní ilà-abẹ́ ni ijọ́ kẹjọ tí ó bí i. Ísáákì sí bí Jákọ́bù, Jákọ́bù sì bí àwọn baba ńlá méjìlá.

9. “Àwọn baba ńlá sí ṣe ìlara Jósẹ́fù, wọ́n sì tà á sí Íjíbítì; ṣùgbọ́n Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀,

10. ó sì yọ ọ́ kúrò nínú ìpọ́njú rẹ̀ gbogbo. Ó sì fún Jósẹ́fù ní ọgbọ́n, ó sì mú kí ó rí ojúrere Fáráò ọba Íjíbítì; òun sì fi jẹ baálẹ̀ Íjíbítì àti gbogbo ilé rẹ̀.

11. “Ìyàn kan sì mú ni gbogbo ilẹ̀ Íjíbítì àti ni Kénánì, àti ìpọ́njú ńlá, àwọn baba wa kò sì rí oúnjẹ.

12. Ṣùgbọ́n nígbà tí Jákọ́bù gbọ́ pé Àlìkámà ń bẹ ni Íjíbítì, ó rán àwọn baba wa lọ lẹ́ẹ̀kínní.

13. Nígbà kejì Jósẹ́fù fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀, a sì tún fi wọ́n hàn fún Fáráò.

14. Lẹ́yìn èyí, Jósẹ́fù ránsẹ́ pe Jákọ́bù baba rẹ̀, àti àwọn ìbátan rẹ̀ wá sọ̀dọ̀ rẹ, gbogbo wọ́n sì tó àrúndínlọ́gọ́rin ènìyàn.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7