Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 26:16-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ṣùgbọ́n dìde, kí o sí fi ẹṣẹ̀ rẹ tẹlẹ̀: nítorí èyí ni mo ṣe farahàn ọ́ láti yàn ọ́ ní ìránṣẹ́ àti ẹlẹ́rìí, fún ohun wọ̀nyí tí ìwọ tí rí nípa mi, àti àwọn ohun tí èmi yóò fí ara hàn fún ọ:

17. Èmi yóò gbà ọ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn rẹ àti lọ́wọ́ àwọn Kèfèrì. Èmi rán ọ ṣí wọn nísìnsìn yìí

18. láti là wọ́n lójú, kí wọn lè yípadà kúrò nínú òkùnkùn sí ìmọ́lẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ agbára Sátanì ṣí Ọlọ́run, kí wọn lè gba ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀, àti ogún pẹ̀lú àwọn tí a sọ di mímọ̀ nípa ìgbàgbọ́ nínú mi.’

19. “Nítorí náà, Àgírípà ọba, èmi kò ṣe àìgbọ́ràn sì ìran ọ̀run náà.

20. Ṣùgbọ́n mo kọ́kọ́ sọ fún àwọn tí ó wà ní Dámásíkù, àti ní Jerúsálémù, àti já gbogbo ilẹ Jùdíà, àti fún àwọn Kèfèrì, kí wọn ronúpìwàdà, kí wọ́n sì yípadà sí Ọlọ́run, kí wọn máa ṣe iṣẹ́ tí ó yẹ sì ìrònúpìwadà.

21. Nítorí nǹkan wọ̀nyí ni àwọn Júù ṣe gbá mi mú nínú tẹ́ḿpílì, tí wọ́n sì ń fẹ́ pá mí.

22. Ṣùgbọ́n bí mo sì tí ri ìrànlọ́wọ́ gbà láti lọ́dọ̀ Ọlọ́run, mo dúró títí ó fí di òní, mo ń jẹ́rìí fún àti èwe àti àgbà, èmi kò sọ ohun mìíràn bí kò ṣe ohun tí àwọn wòlíì àti Móṣè tí wí pé, yóò ṣẹ:

23. Pé, Kírísítì yóò jìyà, àti pé Òun ni yóò jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ láti jíǹde kúrò nínú òkú, Òun ni yóò sí kéde ìmọ́lẹ̀ fún àwọn ènìyàn àti fún àwọn Kèfèrì.”

24. Ní ìkóríta yìí Fẹ́sítúsì kọ dí àwíjàre Pọ́ọ̀lù, ó wí lóhùn rara pé, “Pọ́ọ̀lù, orí rẹ dàrú; ẹ̀kọ́ àkọ́jù rẹ ti dà ọ́ ní orí rú!”

25. Pọ́ọ̀lù da lóhùn wí pé, “Orí mi kò dà rú, Fẹ́sítúsì ọlọ́lá jùlọ; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ òtítọ́ àti ọ̀rọ̀ òye ni èmi ń sọ jáde.

26. Nítorí ọba mọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, níwájú ẹni tí èmi ń ṣọ̀rọ̀ ni àìbẹ̀rù: nítorí mo gbàgbọ́ pé ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò pamọ́ fún un, nítorí tí a kò ṣe nǹkan yìí ní ìkọ̀kọ̀.

27. Àgírípà ọba, ìwọ gba àwọn wòlíì gbọ́ bí? Èmi mọ̀ pé ìwọ gbàgbọ́.”

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 26