Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 16:20-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Nígbà tí wọ́n sì mú wọn tọ àwọn onídájọ́ lọ, wọ́n wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí tí í ṣe Júù, wọ́n ń yọ ìlú wa lẹ́nu jọjọ;

21. Wọ́n sí n kọ́ni ní àṣà tí kò yẹ fún wa, àwa ẹni tí í ṣe ara Romu, láti gbà àti láti tẹ̀lé.”

22. Ọ̀pọ̀ ènìyàn sí jùmọ̀ dìde sì wọn: àwọn olórí sí fà wọ́n láṣọ ya, wọ́n sí pàṣẹ pé, ki a fí ọ̀gọ̀ lù wọ́n.

23. Nígbà tí wọ́n sì lù wọ́n púpọ̀, wọ́n sọ wọ́n sínú túbú, wọ́n kìlọ̀ fún onítúbú kí ó pa wọ́n mọ́ dáradára:

24. Nígbà tí ó gbọ́ irú ìkìlọ̀ bẹ́ẹ̀, ó sọ̀ wọ́n ṣínú túbú tí inú lọ́hùn, ó sí kan àbà mọ wọ́n lẹ́ṣẹ̀.

25. Ṣùgbọ̀n láàrin ọ̀gànjọ́ Pọ́ọ̀lù àti Ṣílà ń gbàdúrà, wọ́n sì ń kọrin ìyìn si Ọlọ́run: àwọn ara túbú sì ń tẹ́tí sí wọn.

26. Lójijì ilẹ̀ mímì ńlá sì mi, tóbẹ́ẹ̀ tí ìpilẹ̀ ile túbú mì tìtì: lọ́gán, gbogbo ilẹ̀kùn sì sí, ìde gbogbo wọn sì tú ṣílẹ̀.

27. Nígbà tí onítúbú si tají, tí o sì ri pé, àwọn ìlẹ̀kùn túbú tí sí sílẹ̀, ó fa idà rẹ̀ yọ, ó sì fẹ́ pa ara rẹ̀, ó ṣebí àwọn ara túbú ti sá lọ.

28. Ṣùgbọ́n Pọ́ọ̀lù gbé ohun rẹ̀ sókè, wí pé, “Má se pa ara rẹ lára: nítorí gbogbo wa ń bẹ níhìn yìí!”

29. Nígbà tí ó sì beere iná, ó bẹ́ wọ inú ilé, ó ń wárìrì, ó wólẹ̀ níwájú Pọ́ọ̀lù àti Sílà.

30. Ó sì mú wọn jáde, ó ní, “Alàgbà, kín ni ki èmi ṣe ki n lè là?”

31. Wọ́n sì wí fún un pé, “Gbá Jéṣù Kírísítì Olúwa gbọ́, a ó sì gbà ọ́ là, ìwọ àti àwọn ará ilé rẹ pẹ̀lú.”

32. Wọ́n sì sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un, àti fún gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀.

33. Ó sì mú wọn ní wákàtí náà lóru, ó wẹ ọgbẹ́ wọn; a ṣi bamitíìsì rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ lójúkan náà.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 16