Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Gálátíà 2:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Fún wọn, a kò tilẹ̀ fí ààyè sílẹ̀, nígbà kan rárá; kí òtítọ́ ìyìn rere lè máa wà títí pẹ̀lú yin.

6. Ṣùgbọ́n ní ti àwọn tí ó dàbí ẹni pàtàkì—ohunkóhun tí ó wù kì wọn já sí, kò jẹ́ nǹkan kan fún mi; Ọlọ́run kò fi bí ẹnìkẹ́ni se rí se ìdájọ́ rẹ̀—àwọn eniyan yìí kò fi ohunkóhun kún ọ̀rọ̀ mi.

7. Ṣùgbọ́n kàkà bẹ́ẹ̀, nígbà tí wọn rí i pé a tí fi ìyìn rere tí àwọn aláìkọlà le mi lọ́wọ́, bí a tí fi ìyìn rere tí àwọn onílà lé Pétérù lọ́wọ́.

8. Nítorí Ọlọ́run, ẹni tí ó ṣiṣẹ́ nínú iṣẹ́ ìránsẹ Pétérù gẹ́gẹ́ bí Àpósítélì sí àwọn Júù, òun kan náà ni ó ṣiṣẹ́ nínú iṣẹ́ ìránsẹ mi gẹ́gẹ́ bí Àpósítélì sí àwọn aláìkọlà.

9. Jákọ́bù, Pétérù, àti Jòhánù, àwọn ẹni tí ó dàbí ọ̀wọ̀n, fún èmi àti Bánábà ni ọwọ́ ọ̀tún ìdàpọ̀ nígbà tí wọ́n rí oore-ọ̀fe tí a fi fún mi, wọ́n sì gbà pé kí àwa náà tọ àwọn aláìkọlà lọ, nígbà ti àwọn náà lọ sọ́dọ̀ àwọn Júù.

10. Ohun gbogbo tí wón bèèrè fún ni wí pé kí a máa rántí àwọn tálákà, ohun kan náà gan-an tí mo ń làkàkà láti ṣe.

Ka pipe ipin Gálátíà 2