orí

  1. 1

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Fílípì 1 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Pọ́ọ̀lù àti Tìmótíù, àwọn ìránṣẹ́ Jésù Kírísítì,Sí gbogbo àwọn ènìyàn-mímọ́ nínú Kírísítì Jésù tí ó wà ní Fílípì, pẹ̀lú àwọn bíṣọ́ọ̀bù àti àwọn díákónì

2. Oore-ọ̀fẹ́ sí yín, àti àlàáfíà, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Olúwa wa Jésù Kírísítì.

Àdúrà Àti Ọpẹ́

3. Mo ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run mi ní gbogbo ìgbà tí mo bá rántí yín:

4. Nínú gbogbo àdúrà mi fún-un yín, èmi ń fi ayọ̀ gbàdúrà,

5. nítorí ìdàpọ̀ yín nínú ìyìn rere láti ọjọ́ kìn-ín-ni wá títí di ìsinsinyìí.

6. Ohun kan yìí ṣáà dá mi lójú pé, ẹni tí ó ti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere nínú yín, yóò ṣe àṣepé rẹ̀ títí di ọjọ́ Jésù Kírísítì:

7. Gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ fún mi láti ro èyí nípa gbogbo yín, nítorí tí mo fi yín sọ́kàn, bí mo tilẹ̀ wà nínú ìdè tàbí ìdáhùn ẹjọ́, àti ìfẹsẹmúlẹ̀ ìyìnrere, gbogbo yín jẹ́ alábàápín oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run pẹ̀lú mi.

8. Nítorí Ọlọ́run ni ẹlẹ́rìí mi, bí mo ti ń ṣàfẹ́rí yín gidigidi nínú ìfẹ́ Jésù Kírísítì.

9. Èyí sì ni àdúrà mi: pé kí ìfẹ́ yín lè máa pọ̀ síwájú àti ṣíwájú síi nínú ìfẹ́ àti ìmọ̀ ìjìnlẹ̀,

10. kí ẹ̀yin kí ó lè dà ohun tí ó dára jùlọ yàtọ̀ mọ̀, kí ẹ sì jẹ́ mímọ́ àti aláìlábàwọ́n títí di ọjọ́ Kírísítì,

11. tí ẹ sì kún fún èso òdodo tí ó ti ọ́dọ̀ Jésù Kírísítì wá—fún ògo àti ìyìn Ọlọ́run.

Ìrírí Pọ́ọ̀lù Nínú Iṣẹ́-Ìránṣẹ́

12. Ǹjẹ́ èmi fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó mọ̀, ará, pé ohun tí ó ẹlẹ̀ sí mi já sí àtẹ̀gùn sí ìlọsíwájú ìyìnrere.

13. Nítorí ìdí èyí, ó ti hàn gbangban sí gbogbo àwọn ẹ̀sọ́ ààfin àti sí àwọn ẹlòmíràn wí pé mo wà nínú ìdè fún Kírísítì.

14. Nítorí ìdè mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ará nínú Olúwa ni ẹ ti mú lọ́kàn le láti sọ̀rọ̀ Ọlọ́run síi pẹ̀lú ìgboyà àti láìbẹ̀rù.

15. Òtítọ́ ni pé àwọn ẹlòmíràn tilẹ̀ ń fi ìjà àti ìlara wàásù Kírísítì, ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn sì ń fi inú rere ṣe é.

16. Àwọn ti ìkẹ́yìn n fi ìfẹ́ ṣe é, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé a ó gbé mi dìde fún ìgbèjà ìyìn rere.

17. Ṣùgbọ́n àwọn ti ìṣáájú ẹ̀wẹ̀ ń fi ìlépa ara ẹni ń wàásù Kírísítì, kì í ṣe pẹ̀lú òótọ́ inú, wọn ń gbérò láti fi ìpọ́njú kún ìdè mi ni.

18. Ṣùgbọ́n ohun tí ó sa ṣe pàtàkì ni pé, bóyá a wàásù pẹ̀lú ètè tó dára tàbí èyí tí kò dára, a ṣsá ń wàásù Kírísítì. Èyí sì ni ayọ̀ mi.Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì máa yọ̀;

19. Nítorí tí mo mọ̀ pé nípa àdúrà yín àti ìrànlọ́wọ́ tí Ẹ̀mí Jésù Kírísítì, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí mi yóò padà já sí ìtúsílẹ̀ mi.

20. Ó jẹ́ ìfojúsọ́nà àti ìrètí mi pé ojú kì yóò tì mí nínú ohunkóhun, ṣùgbọ́n èmi ó ní ìgboyà nísinsìnyìí bí ti ìgbà gbogbo pé ní yíyè, tàbí ní kíkú, a ó gbé ga lára mi.

21. Nítorí, níti èmi, láti wa láàyè jẹ́ Kírísítì, láti kú jẹ́ èrè.

22. Ṣùgbọ́n bí èmi bá sì wà láàyè nínú ara, èyí yóò jásí èrè fún iṣẹ́ mi. Síbẹ̀, kíni èmí yóò yàn? Èmi kò mọ̀?

23. Mo wà ní agbede méjì. Mo fẹ́ràn láti wà pẹ̀lú Kírísítì, èyí tí ó dára jùlọ.

24. Ṣùgbọ́n ó ṣe iyebíye fún yín kí èmi kí ó wà nínú ara.

25. Bí èyí sì ti dá mi lójú, mo mọ̀ pé èmi ó dúró, èmi ó sì máa wà pẹ̀lú yín fún ìtẹ̀síwájú àti ayọ̀ yín nínú ìgbàgbọ́,

26. kí ìbádàpọ̀ mi pẹ̀lú yín lẹ́ẹ̀kan si le ru ayọ̀ yín sókè nínú Kírísítì nítorí mi.

27. Ohun tó wù kí ó ṣẹlẹ̀, ẹ jẹ́ kí iṣẹ́ yín wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyìnrere Kírísítì. pé yálà bí mo tilẹ̀ wá wò yín, tàbí bí èmi kò wá, kí èmi lè máa gbúròó bí ẹ ti ń ṣe, pé ẹ̀yin dúró ṣinṣin nínú Ẹ̀mí kan, ẹ̀yin sì jùmọ̀ n jìjàkadì nítorí ìgbàgbọ́ ìyìn rere, pẹ̀lú ọkàn kan;

28. láìsí ìbẹ̀rẹ̀ àwọn tí ó dojúkọ yin lọ́nà kanna. Èyí sì jẹ́ àmì fún wọn pé a ó pa wọ́n run, a ó sì gbà yín là —èyí tí Ọlọ́run yí ó ṣe.

29. Nítorí a ti fi fún yín nítorí Kírísítì, kì í ṣe láti gbàgbọ́ nínú rẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n láti jìyà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú.

30. Nípa níní ìjàkadì kan náà tí ẹ̀yin ti rí tí èmi là kọjá, ti ẹ sì gbọ́ nísinsinyìí pé mo sì wà nínú rẹ̀.