Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Pétérù 2:6-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Nítorí nínú ìwé mímọ́, ó wí pe:“Kìyèsi i, mo fi pàtàkì òkúta ìgún-ilẹ̀ àṣàyàn,iyebíye, lélẹ̀ ni Síónì:ẹni tí ó bá sì gbà á gbọ́ojú kì yóò tì í.”

7. Báyìí fún ẹ̀yin ti ẹ gbà á gbọ́, ó ṣe iyebíye; ṣùgbọ́n fún àwọn tí kò gbà á gbọ́,“Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀ sílẹ̀,òun ni ó di pàtàkì ìgún-ilé,”

8. àti pẹ̀lú,“Òkúta ìdìgbòlù,àti àpáta ìkọ̀sẹ̀.”Nítorí wọn kọsẹ̀ nípa ṣíṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ náà, sínú èyí tí a gbé yàn wọ́n sí pẹ̀lú.

9. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni ìran tí a yàn Olu àlùfáà, Orílẹ̀ èdè mímọ́, ènìyàn ọ̀tọ̀ ki ẹ̀yin lè fi ọla ń lá ẹni tí ó pè yín jáde kúrò nínú òkùnkùn sínú ìmọ́lẹ̀ ìyanu rẹ̀ hàn:

10. Ẹ̀yin tí kì í ṣe ènìyàn nígbà kan rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ti di ènìyàn Ọlọ́run, ẹ̀yin tí kò rí àánú gbà rí, ṣùgbọ́n nísinsinyìí, ẹ ti rí àánú gbà.

11. Olùfẹ́ ọ̀wọ́n, mo bẹ̀ yín, bí àlejò àti èrò, láti fà sẹ́hìn kúrò nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara, tí ń ba ọkàn jagun;

12. Kí ìwà yín láàrin àwọn aláìkọlà dára; pé, bí wọn ti ń sọ̀rọ̀ yín bí olùṣe búburú, nípa iṣẹ́ rere yín tí wọn ó máa kíyèsí, kí wọ́n lè máa yin Ọlọ́run lógo lọ́jọ́ ti òun ba bẹ̀ wá wò.

13. Ẹ máa tẹríba fún gbogbo ìlànà ènìyàn nítorí ti Olúwa: ì bá à ṣe fún ọba, fún olórí.

14. Tàbí fún àwọn baálẹ̀, fún àwọn tí a rán láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ fún ìgbẹ̀san lára àwọn tí ń ṣe búburú, àti fún ìyìn àwọn tí ń ṣe rere.

15. Ìfẹ́ Ọlọ́run sá ni èyí pé, ní rere í ṣe, kí ẹ lè dẹ́kun ọ̀rọ̀ àìmọ̀kan òmùgọ̀ ènìyàn.

16. Ẹ máa gbé gẹ́gẹ́ bí ẹni òmìnira, ṣùgbọ́n ẹ maṣe lo òmìnira yín láti bo ibi mọ́lẹ̀; ṣùgbọ́n kí ẹ gbé gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Ọlọ́run.

Ka pipe ipin 1 Pétérù 2