Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 11:23-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Nítorí èyí tí èmi gbà lọ́wọ́ Olúwa ni mo ti fi fún un yin. Ní alẹ́ ọjọ́ tí Júdásì fi hàn, Olúwa Jésù Kírísítì mú búrẹ́dí.

24. Lẹ́yìn igbà tí ó ti dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run fún àkàrà náà tan, ó bù ú, ó fi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ gbà kí ẹ sì jẹ, èyí ní ara mi tí a fi fún un yín. Ẹ máa ṣe eléyìí ni rántí mi.”

25. Bákan náà ló mu kọ́ọ̀bù ọtí wáìnì lẹ́yìn oúnjẹ, ó sì wí pé, “Kọ́ọ̀bù yìí ní májẹ̀mú titun nínú ẹ̀jẹ̀ mi, ẹ máa ṣe èyí, nígbàkígbà ti ẹ̀yìn bá ń mu ú, ní ìrántí mi.”

26. Nítorí nígbákùúgbà tí ẹ bá ń jẹ lára àkàrà yìí, tí ẹ sì ǹ mu nínú kọ́ọ̀bù yìí, ni ẹ tún sọ nipa ikú Olúwa. Ẹ máa ṣe eléyìí títí yóò fi padà dé.

27. Nítorí náà tí ẹnikẹ́ni bá jẹ lára àkàrà yìí, tí ẹ sì ń mu nínú kọ́ọ̀bù Olúwa yìí, ní ọ̀nà tí kò bójúmu, yóò jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ sí ara àti ẹ̀jẹ̀ Olúwa.

28. Ìdí nìyìí tí ó fi yẹ kí ènìyàn yẹ ara rẹ̀ wò dáadáa kí ó tó jẹ lára àkàrà nàá àti kí ó tó mu nínú ife náà.

29. Nítorí tí ẹ bá jẹ lára àkàrà, tí ẹ sì mu nínú kọ́ọ̀bù láìyẹ, tí ẹ kò ronú ara Kírísítì áti nǹkan tí ó túmọ̀ sí, ẹ̀ ń jẹ, ẹ sì ń mú ẹ̀bi ìdájọ́ Ọlọ́run wá sórí ara yín.

30. Ìdí nìyìí tí ọ̀pọ̀ yín fi di ẹni tí kò lágbára mọ́, tí ọ̀pọ̀ yín sì ń sàìsàn, àwọn mìíràn nínú yín tilẹ̀ ti sùn.

31. Ṣùgbọ́n tí ẹ bá yẹ ara yín wò dáadáa, kí ẹ tó jẹ ẹ́, a kì yóò dá yín lẹ́jọ́.

32. Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀ ti Olúwa bá tilẹ̀ ṣe ìdájọ́ wa, tí ó sì jẹ wá níyà nítorí àwọn àṣìṣe wa, ó dára bẹ́ẹ̀, ó ń ṣe bẹ́ẹ̀, kí a má baà dá wa lẹ́jọ́, kí a sì pa wá run pẹ̀lú ayé.

33. Nítorí náà, ẹ̀yin arákùnrin mi ọ̀wọ́n, nígbàkúùgbà ti ẹ bá péjọ láti jẹ́ oúnjẹ alẹ́ Olúwa, tàbi fún ìsìn oúnjẹ alẹ́ Olúwa, ẹ dúró de ara yín.

34. Bí ebi bá ń pa ẹnikẹ́ni nínú yin, kí ó jẹun láti ilé wá, kí ó má baá mú ìjìyà wá sórí ara rẹ̀ nígbà tí ẹ bá pé jọ.Tí mo bá dé, èmi yóò máa sọ̀rọ̀ lórí àwọn kókó ọ̀rọ̀ ìyókù tí n kò ì ti fẹnu bà lẹ́sẹsẹ.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 11