Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 1:6-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Nítorí ẹ̀rí wa nínú Kírísítì ni a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nínú yín.

7. Nítorí náà ẹ̀yin kò ṣe aláìní nínú èyíkéyì ẹ̀bùn ẹ̀mí, bí ẹ̀yin ṣe ń retí ìfarahàn Olúwa wa Jésù Kírísítì.

8. Òun yóò sì mú yín dúró títí dé òpin, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ́ aláìlábùkù ní ọjọ́ Olúwa wa Jésù Kírísítì.

9. Ọlọ́run, nípaṣẹ̀ ẹni ti a pè yín sínú ìdàpọ̀ pẹ̀lú Ọmọ rẹ̀ Jésù Kírísítì Olúwa wa, jẹ́ Olótítọ́.

10. Mo bẹ̀ yín ẹ̀yin ara, ní orúkọ Olúwa wa Jésù Kírísítì, pé kí gbogbo yín fohùnsọ̀kan kí ó máa ṣe sí ìyàpá láàrin yín, àtipé kí a lè ṣe yín pé ní inú àti ìmọ̀ kan náà.

11. Ẹ̀yin ará mi, àwọn kan láti ilé Kiloe sọ di mímọ̀ fún mi pé ìjà ń bẹ́ láàrin yín.

12. Ohun tí mo ń sọ ni pé: Olúkúlùku yín ń wí pé, “Èmí tẹ̀lé Pọ́ọ̀lù”; “Èmi tẹ̀lé Àpólò”; òm̀íràn, “Èmi tẹ̀lé Kéfà, ìtúmọ̀, Pétérù”; àti ẹlòmìíràn, “Èmi tẹ̀lé Kírísítì.”

13. Ǹjẹ́ a há pín Jésù bí? Ṣé a kan Pọ́ọ̀lù mọ́ àgbélébùú fún un yín bí? Ǹjẹ́ a tẹ̀yín bọmi yín ní orúkọ Pọ́ọ̀lù bí?

14. Inú mi dún púpọ̀ pé èmi kò tẹ ẹnikẹ́ni nínú yín bọmi yàtọ̀ sí Kírísípù àti Gáíù.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 1