Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 1:10-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Mo bẹ̀ yín ẹ̀yin ara, ní orúkọ Olúwa wa Jésù Kírísítì, pé kí gbogbo yín fohùnsọ̀kan kí ó máa ṣe sí ìyàpá láàrin yín, àtipé kí a lè ṣe yín pé ní inú àti ìmọ̀ kan náà.

11. Ẹ̀yin ará mi, àwọn kan láti ilé Kiloe sọ di mímọ̀ fún mi pé ìjà ń bẹ́ láàrin yín.

12. Ohun tí mo ń sọ ni pé: Olúkúlùku yín ń wí pé, “Èmí tẹ̀lé Pọ́ọ̀lù”; “Èmi tẹ̀lé Àpólò”; òm̀íràn, “Èmi tẹ̀lé Kéfà, ìtúmọ̀, Pétérù”; àti ẹlòmìíràn, “Èmi tẹ̀lé Kírísítì.”

13. Ǹjẹ́ a há pín Jésù bí? Ṣé a kan Pọ́ọ̀lù mọ́ àgbélébùú fún un yín bí? Ǹjẹ́ a tẹ̀yín bọmi yín ní orúkọ Pọ́ọ̀lù bí?

14. Inú mi dún púpọ̀ pé èmi kò tẹ ẹnikẹ́ni nínú yín bọmi yàtọ̀ sí Kírísípù àti Gáíù.

15. Nítorí náà kò sí ẹni tí ó lè sọ pé òun ṣe ìtẹ̀bọmi ní orúkọ èmi fúnraara mi.

16. (Bẹ́ẹ̀ ni, mo tún tẹ ìdílé Sítéfánà bọmi; lẹ́yìn èyí, èmí kò rántí pé mo tẹ ẹnikẹ́ni bọmi mọ́ níbikíbi).

17. Nítorí Kírísítì kò rán mi láti máa ṣe ìtẹ̀bọmi, ṣùgbọ́n Ó rán mi láti máa wàásù ìyìn rere: kì í ṣe nípa ọgbọ́n ènìyàn, kí a máa ṣe sọ àgbélébú Kírísítì dí aláìlágbára.

18. Nítorí pé òmùgọ̀ ni ọ̀rọ̀ àgbélébùú jẹ́ sí àwọn tí ń sègbé, ṣùgbọ́n fún àwa tí a ń gbàlà ó jẹ́ agbára Ọlọ́run

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 1