Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sekaráyà 7:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dáríúsì ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekaráyà wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kísíléfì tí ń se oṣù kẹsàn-án.

2. Nígbà tí wọ́n rán Sérésérì àti Régémélékì, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojú rere Olúwa.

3. Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù kárùnún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”

4. Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,

5. “Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti fún àwọn àlùfáà pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin gbààwẹ̀, tí ẹ sì ṣọ̀fọ̀ ní oṣù karùnún àti keje, àní fun àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, ǹjẹ́ èmi ni ẹ̀yin hà ń gbààwẹ̀ yín fún?

6. Nígbà tí ẹ sì jẹ, àti nígbà tí ẹ mu, fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin jẹ, àti fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin mú bí?

7. Wọ̀nyí kọ́ ni ọ̀rọ̀ ti Olúwa ti kígbe láti ọdọ àwọn wòlíì ìṣáájú wá, nígbà tí a ń gbé Jérúsálẹ́mù, tí ó sì wà ní àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀ tí ó yí i káàkiri, nígbà tí a ń gbé gúsù àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.’ ”

8. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sekaráyà wá, wí pé:

9. “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: ‘Ṣe ìdájọ́ òtítọ́, kí ẹ sì ṣe àánú àti iyọ́nú olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀.

Ka pipe ipin Sekaráyà 7