Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sekaráyà 2:4-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọdọmọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jérúsálẹ́mù bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun-ọ̀sìn inú rẹ̀.

5. Olúwa wí pé, Èmí ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrin rẹ̀.’

6. “Áà! Áà! Sá kúrò ni ilẹ̀ àriwá, ni Olúwa wí; nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín kákiri,” ni Olúwa wí.

7. “Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, Ìwọ Síonì, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Bábílónì gbé.”

8. Nítorí bayìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.

9. Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ikogun fún iránṣẹ́ wọn: ẹ̀yín yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.

10. “Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Síónì: Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárin rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Ka pipe ipin Sekaráyà 2