Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sekaráyà 14:3-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ, yóò sì bá àwọn orílẹ̀-èdè náa jà, gẹ́gẹ́ bí í ti ìjà ní ọjọ́ ogun.

4. Ẹṣẹ̀ rẹ̀ yóò sì dúró ni ọjọ́ náà lórí òkè Ólífì, tí ó wà níwájú Jérúsálẹ́mù ni ila-oòrùn, òkè Ólífì yóò sì làá sí méjì, sí ìhà ilà-oòrùn àti ìhà ìwọ̀-oòrun, àfonífojì ńláńlá yóò wà: ìdajì òké náà yóò sì sí síhà àríwá, àti ìdajì rẹ̀ síhà gúṣù.

5. Ẹ̀yin ó sì ṣá sí àfonífojì àwọn òkè mi: nítorí pé àfonífojì òkè náà yóò dé Àṣàlì: nítòòtọ́, ẹ̀yin ó ṣá bí ẹ tí ṣá fún ìmímì-ilẹ̀ ni ọjọ́ Úṣáyà ọba Júdà: Olúwa Ọlọ́run mi yóò sì wá, àti gbogbo àwọn Ẹni-mímọ́ pẹ̀lú rẹ̀.

6. Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìmọ́lẹ̀ kì yóò mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ṣókùnkùn.

7. Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ ọjọ́ kan mímọ́ fún Olúwa, kì í ṣe ọ̀ṣán, kì í ṣe òru; ṣùgbọ́n yóò ṣe pé, ni àṣálẹ́ ìmọ́lẹ̀ yóò wà.

8. Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, omi ìyè yóò tí Jérúsálẹ́mù ṣàn lọ; ìdájì wọn sìhà òkun ilà-oòrùn, àti ìdájì wọn síhà okùn ẹ̀yìn: nígbà ẹ̀rùn àti nígbà òtútù ni yóò rí bẹ́ẹ̀.

9. Olúwa yóò sì jọba lórí gbogbo ayé; ni ọjọ́ náà ni Olúwa kan yóò wa orúkọ rẹ̀ nìkan náà ni orúkọ.

Ka pipe ipin Sekaráyà 14