orí

  1. 1
  2. 2
  3. 3

Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sefanáyà 3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

Ọjọ́ Ìwájú Jérúsálẹ́mù

1. Ègbé ni fún ìlú aninilára,ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.

2. Òun kò gbọ́ràn sí ẹnikẹ́ni,òun kò gba ìtọ́ni,òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa,bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.

3. Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìun tí ń ké ramúramù,àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkokò àṣálẹ́ ni wọn,wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.

4. Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga,wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn.Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́,wọ́n sì rú òfin.

5. Olúwa ni àárin rẹ̀ jẹ́ olódodo;kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà.Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀,kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun,ṣíbẹ̀ àwọn aláìsòótọ́ kò mọ ìtìjú.

6. “Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò,ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́.Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní ihàtóbẹ́ẹ̀ tí ẹnìkan kan kò kọjá níbẹ̀.Ìlú wọn parun tóbẹ́ẹ̀ tí kò síẹnikan tí yóò sẹ́kù,kò sì ní sí ẹnìkan rárá.

7. Èmi wí fún ìlú náà wí pé‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi,ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúròbí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n níyà tó.Ṣùgbọ́n ṣíbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtaraláti ba iṣẹ́ wọn jẹ́.

8. Nítorí náà ẹ dúró dèmi,” ni Olúwa wí,“títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò dìde si ohun ọdẹ; nítoríìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kíèmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti rú ìbínú jádesórí wọn, àní gbogbo ibínú gbígbóná mi.Nítorí, a ó fi iná owú ibínú jẹ gbogbo ayé run.

9. “Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́,nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa,láti fi ọkàn kan sìnín.

10. Láti òkè odò Etiópíà,àwọn olùsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká,yóò mú ọrẹ wá fún mi.

11. Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútìnítorí gbogbo ìsẹ́ni tí ó ti ṣesí mi, nígbà náà ni èmi yóò mukúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn.Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ní òkè mímọ́ mi.

12. Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútùàti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárin rẹ̀,wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.

13. Àwọn ìyókù Ísírẹ́lì kì yóò hùwàibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké,bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè níẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rù bà wọ́n.”

14. Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Síónì,kígbé sókè, ìwọ Ísírẹ́lì!Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn,ìwọ ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù.

15. Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nìkúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀ta rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Ísírẹ́lì wà pẹ̀lú rẹ,Ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.

16. Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jérúsálẹ́mù pé,“Má ṣe bẹ̀rù Síónì;má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.

17. Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ,Ó ní agbára láti gbà ọ là.Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀;Yóò tún ọ se nínú ìfẹ́ rẹ̀,Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”

18. “Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ̀ fún àjọ mímọ́ jọ,àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀;àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.

19. Ní àkókò náàni èmi yóò dojúkọ àwọntí ń ni yín lára,èmi yóò gba atiro là,èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ,èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn nígbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.

20. Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ;Nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé.Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yínláàárin gbogbo ènìyàn àgbáyé,nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yínpadà bọ sípò ní ojú ara yín,”ni Olúwa wí.