Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 13:6-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Nígbà náà ni obìnrin náà tọ ọkọ rẹ̀ lọ, o sì sọ fún un wí pé, “Èniyàn Ọlọ́run kan tọ̀ mí wá. Ó jọ ańgẹ́lì Ọlọ́run, ó bà ènìyàn lẹ́rù gidigidi. Èmi kò béèrè ibi tí ó ti wá, òun náà kò sì sọ orúkọ rẹ̀ fún mi.

7. Ṣùgbọ́n ó sọ fún mi wí pé, ‘Ìwọ yóò lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan, fún ìdí èyí, má ṣe mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ má se jẹ ohunkóhun tí í ṣe aláìmọ́, nítorí pé Násírì Ọlọ́run ni ọmọ náà yóò jẹ́ láti ọjọ́ ìbí rẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.’ ”

8. Nígbà náà ni Mánóà gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Háà Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ènìyàn Ọlọ́run tí ìwọ rán sí wa padà tọ̀ wá wá láti kọ́ wa bí àwa yóò ti ṣe tọ́ ọmọ tí àwa yóò bí náà.”

9. Ọlọ́run fetí sí ohùn Mánóà, ańgẹ́lì Ọlọ́run náà tún padà tọ obìnrin náà wá nígbà tí ó wà ní oko: Ṣùgbọ́n ọkọ rẹ̀ Mánóà kò sí ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.

10. Nítorí náà ni obìnrin náà ṣe yára lọ sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó fara hàn mí ní ọjọ́sí ti tún padà wá.”

11. Mánóà yára dìde, ó sì tẹ̀lé aya rẹ̀, nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ọkùnrin náà ó ní, “Ǹjẹ́ ìwọ ni o bá obìnrin yìí sọ̀rọ̀?”Ọkùnrin náà dáhùn pé “Èmi ni.”

12. Mánóà bi ọkùnrin náà pé, “Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ kí ni yóò jẹ́ ìlànà fún ìgbé ayé àti iṣẹ́ ọmọ náà?”

13. Ańgẹ́lì Olúwa náà dáhùn wí pé, “Aya rẹ gbọdọ̀ ṣe gbogbo ohun tí mo ti sọ fún un

14. kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti inú èṣo àjàrà jáde wá, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ mu wáìnì tàbí àwọn ọtí líle mìíràn tàbí jẹ ohunkóhun tí ó bá jẹ́ aláìmọ́. Ó ní láti ṣe ohun gbogbo tí mo ti pa láṣẹ fún un.”

15. Mánóà sọ fún ańgẹ́lì Olúwa náà pé, “Jọ̀wọ́ dára dúró títí àwa yóò fi pèṣè ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan fún ọ.”

16. Ańgẹ́lì Olúwa náà dá Mánóà lóhùn pé, “Bí ẹ̀yin tilẹ̀ dá mi dúró, Èmi kì yóò jẹ ọ̀kankan nínú oúnjẹ tí ẹyin yóò pèṣè. Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá fẹ́ ẹ pèṣè ọrẹ ẹbọ ṣíṣun, kí ẹ sì fi rúbọ sí Olúwa.” (Mánóà kò mọ̀ pé ańgẹ́lì Olúwa ní i ṣe.)

17. Mánóà sì béèrè lọ́wọ́ ańgẹ́lì Olúwa náà pé, “Kí ni orúkọ rẹ, kí àwa bá à lè fi ọlá fún ọ nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ bá ṣẹ?”

Ka pipe ipin Onídájọ́ 13