Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 12:5-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Àwọn ará Gílíádì gba àbáwọdò Jọ́dánì tí wọ́n máa gbà lọ sí Éfúráímù, nígbàkígbà tí àwọn ará Éfúráímù bá wí pé, “Jẹ́ kí ń sá lọ sí òkè,” lọ́hùn ún àwọn ará Gílíádì yóò bi í pé, “Ṣé ará Éfúráímù ni ìwọ ń ṣe?” Tí ó bá wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́,”

6. wọ́n ó wí fún un pé, “Ó dá à wí pé ‘Ṣhíbólétì.’ ” Tí ó bá ní, “Síbólé,” tì torí pé kò ní mọ̀ọ́ pé dáadáa, wọ́n á mú-un wọn, a sì pa á ni àbáwọdò Jọ́dánì. Àwọn ará Éfúráímù tí wọn pa ní àkókò yìí jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìléní-ogójì ọkùnrin.

7. Jẹ́fítà ṣe ìdájọ́ Ísírẹ́lì ní ọdún mẹ́fà. Lẹ́yìn náà Jẹ́fítà ará Gílíádì kú, wọ́n sì sin ín sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú Gílíádì.

8. Lẹ́yìn Jẹ́fítà, Íbísánì ará Bẹ́tílẹ́hẹ́mù ṣe ìdájọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

Ka pipe ipin Onídájọ́ 12