Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 36:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn olórí ìdílé Gílíádì, ọmọkùnrin Mákírì ọmọ Mánásè tí ó wá láti ara ìdílé ìrán Jósẹ́fù wá, wọ́n sì sọ̀rọ̀ níwájú Mósè àti àwọn olórí, àwọn ìdílé Ísírẹ́lì.

2. Wọ́n sọ pé, “Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún olúwa mi láti fi ilẹ̀ yìí fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ogún nípa kèké ṣíṣẹ́. Ó pa á láṣẹ fún ọ láti fi ogún Ṣélófíhádì arákùnrin wa fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.

3. Wàyí, tí wọn bá fẹ́ ọkùnrin láti ẹ̀yà Ísírẹ́lì mìíràn; nígbà náà a ó gba ogún un wọn kúrò nínú ogún ìran wa, a ó sì fi kún ogún ẹ̀yà tí a fẹ́ wọn sí. Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gbàá kúrò nínú ìpín ilẹ̀ ogún ti wa.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 36