Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 28:6-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Èyí ni ẹbọ sísun gbogbo ìgbà tí a fi lẹ́lẹ̀ ní òkè Sínáì gẹ́gẹ́ bí olóòrùn dídùn ẹbọ tí a fi iná sun fún Olúwa pẹ̀lú iná.

7. Àfikún ọrẹ ohun mímu rẹ gbọdọ̀ jẹ́ ìdámẹ́rin ti hínì dídé omi mímu tí ó kan pẹ̀lú ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀dọ́ àgùntàn. Da ẹbọ mímu náà síta sí Olúwa ní ibi mímọ́.

8. Pèsè ọ̀dọ́ àgùntàn kejì ní àfẹ̀mọ̀júmọ́, pẹ̀lú oríṣìí ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu èyí tí ó pèsè ní òwúrọ̀, èyí ni ẹbọ tí a fi iná ṣe, olóòrùn dídùn sí Olúwa.

9. “ ‘Ní ọjọ́ ìsinmi, pèsè akọ ọ̀dọ́ àgùntàn méjì olọ́dún kan tí kò lábùkù, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu àti ẹbọ ohun jíjẹ tí i ṣe ìdá méjì nínú ìdámẹ́wàá òṣùwọn ìyèfun ìyẹ̀fun tí a fi òróró pò.

10. Èyí ni ẹbọ sísun fún gbogbo ọjọ́ ìsinmi kọ̀ọ̀kan, ní àfikún pẹ̀lú ẹbọ sísun àti ẹbọ ohun mímu.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 28