Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 27:18-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mósè pé, “Mú Jóṣúà ọmọ Núnì, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.

19. Jẹ́ kí ó dúró níwájú Élíásárì àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Ísírẹ́lì kí o sì fi àsẹ fún un ní ojú wọn.

20. Fún un ní ara àwọn àṣẹ rẹ kí gbogbo ìlú Ísírẹ́lì kí ó lè gbọ́ràn sí i lẹ́nu.

21. Kí ó dúró níwájú Élíásárì àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Úrímù níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Ísírẹ́lì yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”

22. Mósè sì se gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Jóṣúà ó sì mú kí ó dúró níwájú Élíásárì àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.

23. Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 27