Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 27:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọmọbìnrin Ṣélóféhátì ọmọ Héférì, ọmọ Gílíádì, ọmọ Mákírì ọmọ Mánásè tó jẹ́ ìdílé Mánásè, ọmọ Jósẹ́fù wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Málà, Nóà, Hógílà, Mílíkà àti Tásà.

2. Wọ́n súnmọ́ ẹnu ọ̀nà Àgọ́ Ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mósè, àti Élíásérì àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,

3. “Baba wa kú sí ihà. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kórà tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, Ṣùgbọ́n ó kú nítórí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.

4. Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítórí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrin àwọn arakùnrin baba wa.”

5. Nígbà náà Mósè mú ọ̀rọ̀ wọn wá ṣíwájú Olúwa.

6. Olúwa sì wí fún un pé,

7. “Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Ṣélófénátì ń sọ tọ̀nà. Ó gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.

8. “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 27