Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 26:44-58 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

44. Ti àwọn ọmọ Ásérì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:ti Ímínà, ìdílé àwọn ọmọ Ímínà;ti Íṣífì, ìdílé àwọn ọmọ Íṣífì;ti Béríà, ìdílé àwọn ọmọ Béríà;

45. Ti àwọn ọmọ Béríà:ti Hébérì, ìdílé àwọn ọmọ Hébérì;ti Mákíẹ́lì, ìdílé àwọn ọmọ Mákíẹ́lì.

46. (Orúkọ ọmọ Áṣérì obìnrin nì jẹ́ Ṣérà.)

47. Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Áṣérì gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbéje (53,400).

48. Ti àwọn ọmọ Náfítalì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:ti Jásélì, ìdílé àwọn ọmọ Jásélì:ti Gúnì, ìdílé àwọn ọmọ Gúnì;

49. ti Jésérì, ìdílé àwọn ọmọ Jéṣérì;ti Ṣílémù, ìdílé àwọn ọmọ Ṣilemù.

50. Wọ̀nyí ni ìdílé ti Náfítalì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbéje (45,400).

51. Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́, ó lé ẹgbẹ̀sán ó dín àádọ́rin (601,730).

52. Olúwa sọ fún Mósè pé,

53. “Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn

54. Fún àwọn ọ̀pọ̀ ni kí ìwọ ó fún ní ogún ìlú púpọ̀ àti fún àwọn tí ó kéré ni kí ìwọ ó fi kékeré fún, ẹnìkọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ gba ogún ìbí tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí a kọ.

55. Rí dájú pé ilẹ̀ yìí gbọdọ̀ jẹ́ fífi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọn sì ti pọ̀ tó. Gẹ́gẹ́ bí orúkọ ẹ̀yà àwọn baba wọn ni kí wọn kí ó ni ín.

56. Olúkúlùkù ogún ìní ni a gbọdọ̀ fi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti pọ̀ tó láàrin ńlá àti kékeré.”

57. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Léfì tí a kà nínú wọn gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:ti Gáṣónì, ìdílé àwọn ọmọ Gáṣónì;ti Kóhátì, ìdílé àwọn ọmọ Kóhátì;ti Mérárì, ìdílé àwọn ọmọ Mérárì.

58. Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Léfì;ìdílé àwọn ọmọ Líbínì,ìdílé àwọn ọmọ Hébírónì,ìdílé àwọn ọmọ Málì,ìdílé àwọn ọmọ Múṣì,ìdílé àwọn ọmọ Kórà.(Kóhátì ni baba Ámírámù,

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 26