Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 26:10-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ilẹ̀ sì la ẹnu rẹ̀, ó sì gbé wọn mì pọ̀ pẹ̀lú Kórà, nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kú níbi tí iná ti run àwọn àádọ́tàlérúgba ọkùnrin (250). Tí wọ́n sì di àmì ìkìlọ̀.

11. Àwọn ọmọ Kórà, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.

12. Àwọn ọmọ ìrán Símónì bí ìdílé wọn:ti Némúélì, ìdílé Némúélì;ti Jámínì, ìdílé Jámínì;ti Jákínì, ìdílé Jákínì;

13. ti Ṣérà, ìdílé Ṣérà;tí Ṣọ́ọ̀lù, ìdílé Ṣọ́ọ̀lù.

14. Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Símónì, ẹgbàámọ́kànlá ó lé igba. (22,200) ọkùnrin.

15. Àwọn ọmọ Gádì bí ìdílé wọn:ti Ṣéfónì, ìdílé Ṣéfónì;ti Hágígì, ìdílé Hágígì;ti Ṣúnì, ìdílé Ṣúnì;

16. ti Ósínì, ìdílé Ósíní;ti Érì, ìdílé Érì;

17. ti Árédì, ìdílé Árédì;ti Árólì, ìdílé Árólì.

18. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gádì tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (40,500).

19. Àwọn ọmọ Júdà ni Érì àti Ónánì, ṣùgbọ́n Érì àti Ónánì kú ní ilẹ̀ Kénánì.

20. Àti àwọn ọmọ Júdà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:ti Ṣélà, ìdílé Ṣélà;ti Pérésì, ìdílé Pérésì;ti Sérà, ìdílé Ṣérà.

21. Àwọn ọmọ Pérésì:ti Hésírónì, ìdílé Hésírónì;ti Hámúlù, ìdílé Hámúlù.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 26