Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 21:10-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tẹ̀ṣíwájú wọ́n sì péjọ sí Óbótì.

11. Wọ́n gbéra ní Óbótì wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-àbárímù, ní ihà tí ó kọjú sí Móábù ní ìdojúkọ ìlà oòrùn.

12. Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Sérédì.

13. Wọ́n gbéra kúrò níbẹ̀ wọ́n sì pa ibùdó sí ẹ̀bá ọ̀nà Ánónì, tí ó wà ní Ìfà-gùn ihà tó kángun sí ibi tí ilẹ̀ àwọn ọmọ Ámórì wa. Ánónì jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Móábù, láàrin Móábù àti Ámórì.

14. Ìdí nì yìí tí ìwé ogun Olúwa ṣe wí pé:“…Wáhébù ní Súpà, òkun pupa àtiní odò Ánónì

15. àti ní isà odò tí ó darí sí ibùjókòó Árítí ó sì fara ti ìpìnlẹ̀ Móábù.”

16. Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Béérì, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mósè, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”

17. Nígbà náà ni Ísírẹ́lì kọ orin yìí pé:“Sun jáde, ìwọ kànga!Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,

18. Nípa kanga tí àwọn ọmọ aládé gbẹ́,nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ẹ:tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fiọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.”Nígbà náà wọ́n kúrò láti ihà lọ sí Mátanà,

19. láti Mátanà lọ sí Náhálíẹ́lì, láti Náhálíẹ́lì lọ sí Bámótì,

20. àti láti Bámótì lọ sí àfonífojì ní Móábù níbi tí òkè Písígà, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí ihà.

21. Ísírẹ́lì rán oníṣẹ́ láti sọ fún Síhónì ọba àwọn ará Ámórì wí pé:

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 21