Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 14:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sunkún ní òru ọjọ́ náà.

2. Gbogbo ọmọ Ísírẹ́lì sì kùn sí Mósè àti Árónì, gbogbo ìjọ ènìyàn Ísírẹ́lì sì wí fún wọn pé; “Àwa ì bá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Éjíbítì. Tàbí kí a kúkú kú sínú ihà yìí.

3. Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá?, Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Éjíbítì?”

4. Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Éjíbítì.”

5. Nígbà náà ni Mósè àti Árónì dojú bolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Ísírẹ́lì.

6. Jóṣúà ọmọ Núnì àti Kélẹ́bù ọmọ Jéfúnè, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.

7. Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Ísírẹ́lì pé, “Ìlẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọpọ̀.

8. Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń ṣàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 14