Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemáyà 9:18-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Kódà nígbà tí wọ́n yá ère dídá (ère ọmọ màlúù) fún ara wọn, tí wọ́n sì wí pé, Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Éjíbítì wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì.

19. “Nítorí àánú ńláà rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní ihà. Ní ọ̀sán ọ̀pọ̀ ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀pọ̀ iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn.

20. Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá mánà rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òrùngbẹ.

21. Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní ihà; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹṣẹ̀ wọn kò wú.

22. “Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀ èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Ṣíhónì aráa Hésíbónì àti ilẹ̀ ógù ọba Báṣánì.

23. Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀

24. Àwọn ọmọ wọn wọ inú un rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn aráa Kénánì, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájúu wọn; ó fi àwọn aráa Kénánì lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n.

Ka pipe ipin Nehemáyà 9