Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Náhúmù 3:7-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Kò sí ṣe pé, gbogbo àwọn tí ó ba sì wò ọ́ yóò sì káàánú fún ọ, wọn yóò sì wí pé,‘Nínéfè ṣòfò: Ta ni yóò kẹ́dùn rẹ?’Níbo ni èmi o ti wá olùtùnú fún ọ?”

8. Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Tébésì lọ,èyí tí ó wà ní ibi odò, Náílìtí omi sì yí káàkiri?Odò náà sì jẹ́ ààbò rẹ̀,omi si jẹ́ odi rẹ̀.

9. Etiópíà àti Éjíbítì ni agbára rẹ, kò sí ní òpin;Pútì àti Líbíà ni àwọn olùgbèjà rẹ̀.

10. Ṣíbẹ̀ ṣíbẹ̀ a kó o ní ìgbèkùno sì lọ sí oko ẹrú.Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ̀ ni a ó fọ́ mọ́lẹ̀ní orí ìta gbogbo ìgboro.Wọ́n sì di ìbò nítorí àwọn ọlọ́lá rẹ̀ ọkùnrin,gbogbo àwọn ọlọ́lá rẹ ni a sì fi ẹ̀wọ̀n dè

11. Ìwọ pẹ̀lú yóò sì mu àmupara;a ó si fi ọ́ pamọ́ìwọ pẹ̀lú yóò máa ṣe àfẹ́rí ààbò nítorí ti ọ̀tá náà.

12. Gbogbo ilé-ìṣọ́ agbára rẹ yóò dàbí igi ọ̀pọ̀tọ́pẹ̀lú àkọ́pọ́n èso wọn;Nígbà tí wọ́n bá ń gbọ̀n wọ́n,ọ̀pọ̀tọ́ yóò sì bọ́ sí ẹnu àwọn ọ̀jẹun.

13. Kíyè sí,Obínrin ni àwọn ènìyàn rẹ ní àárin!Ojú ibodè rẹ ní a ó sí sílẹ̀ gbagada,fún àwọn ọ̀tá rẹ̀;iná yóò jó ilẹ̀ rẹ

14. Ìwọ pọn omi de ìhámọ́,mú ile ìsọ́ rẹ lágbára sí iwọ inú amọ̀kí o sì tẹ erùpẹ̀,kí ó sì tún ibi tí a ti ń sun bíríkì-amọ̀ ṣe kí ó le.

15. Níbẹ̀ ni iná yóò ti jó ọ́ run;Idà yóò sì ké ọ kúrò,yóò sì jẹ ọ́ bí i kòkòrò,yóò sì sọ ara rẹ̀ di púpọ̀ bí i tata,àní, di púpọ̀ bí eṣú!

16. Ìwọ ti sọ àwọn oníṣòwò rẹ di púpọ̀títí wọn yóò ṣe pọ̀ ju ìràwọ̀ oju ọ̀run lọKòkòrò na ara rẹ̀ó sì fò lọ.

17. Àwọn aládé rẹ̀ dàbí eṣú,àwọn ọ̀gágun rẹ dàbí ẹlẹ́ǹgà ńlá,èyí ti ń dó sínú ọgbà la ọjọ́ òtútù,ṣùgbọ́n nígbà tí òòrùn jáde, wọ́n sá lọẹnìkan kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé wà.

Ka pipe ipin Náhúmù 3