Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 6:5-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. tàbí ohunkóhun tó búra èké lé lórí. Ó gbọdọ̀ dá gbogbo rẹ̀ padà ní pípé, kí ó fi ìdá márùn ún iye rẹ̀ kún, kí ó sì dá gbogbo rẹ̀ padà fún ẹni tí ó ni í, ní ọjọ́ tó bá ń rú ẹbọ ẹ̀bi rẹ̀.

6. Fún ìtanràn rẹ̀, ó gbọdọ̀ mú àgbò kan láti inú agbo ẹran wá fún àlùfáà, àní ṣíwájú Olúwa, ọrẹ fún ẹ̀ṣẹ̀ àgbò aláìlábùkù, tó sì níye lórí bí iye owó ibi mímọ́.

7. Báyìí ní àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún un ètùtù ìwẹ̀nùmọ́ níwájú Olúwa, a ó sì dárí jìn-ní nítorí ohun tó ti ṣe tó sì mú-un jẹ̀bi.”

8. Olúwa sọ fún Mósè pé:

9. “Pàṣẹ fún Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé: Èyí ni ìlànà fún ẹbọ sísun; ẹbọ sísun gbọdọ̀ wà lórí pẹpẹ láti alẹ́ di òwúrọ̀, kí iná sì máa jó lórí pẹpẹ

10. kí àlùfáà sì wọ èwù funfun rẹ̀ pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ lára rẹ̀, yóò sì kó eérú tó wà nibi ẹbọ sísun tí iná ti jó lórí pẹpẹ, sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ.

11. Nígbà náà ni yóò bọ́ aṣọ rẹ̀, yóò sì wọ òmíràn, yóò wá gbé eérú náà lọ sí ẹ̀yìn ibùdó níbi tí a kà sí mímọ́.

Ka pipe ipin Léfítíkù 6