Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 8:30-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Nígbà náà ni Jóṣúà mọ pẹpẹ kan fún Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì, ní òkè Ébálì,

31. gẹ́gẹ́ bí Móṣè ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Ó sì kọ́ ọ́ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú Iwé Òfin Móṣè, pẹpẹ odindi òkúta, èyí tí ẹnìkan kò fi ohun èlò irin kàn rí. Wọ́n sì rú ọrẹ ẹbo ṣísun àti ọrẹ àlàáfíà ní orí i rẹ̀ sí Olúwa.

32. Níbẹ̀ ní ojú àwọn ará Ísírẹ́lì, Jósúà sì ṣe àdàkọ òfin Mósè èyí tí ó ti kọ sí ara òkúta náà.

33. Gbogbo Ísírẹ́lì, àlejò àti ọmọ ìlú, pẹ̀lú àwọn àgbà, olórí àti onídàájọ́ dúró ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àpótí ẹ̀rí Olúwa tí ó kọjú sí àwọn àlùfáà tí ó rù ú, tí wọ́n jẹ́ ọmọ Léfì. Ìdajì àwọn ènìyàn náà dúró ní Òkè Gérísímù, àwọn ìdajì si dúró ni òkè Ébálì, gẹ́gẹ́ bí Mósè ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ rí, pé kí wọn súre fún àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì.

34. Lẹ́yìn èyí, Jóṣúà sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin ìbùkún àti ègún-gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú Ìwé Òfin.

Ka pipe ipin Jóṣúà 8