Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 8:20-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Àwọn ọkùnrin Áì bojú wo ẹ̀yìn, wọ́n rí èéfín ìlú náà ń gòkè lọ sí ọ̀run, ṣùgbọ́n wọn kò rí, àyè láti sá àsálà lọ sí ibìkan kan, nítorí tí àwọn ará Ísírẹ́lì tí wọ́n tí ń sálọ sí ihà ti yípadà sí àwọn tí ń lépa wọn.

21. Nígbà tí Jóṣúà àti gbogbo àwọn ará Ísírẹ́lì rí i pé àwọn tí ó ba ti gba ìlú náà, tí èéfín ìlú náà sì ń gòkè, wọ́n yí padà wọ́n sì kọlu àwọn ọkùnrin Áì.

22. Àwọn ọmọ ogun tí ó ba náà sì yípadà sí wọn láti inú ìlú náà, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wà ní agbede-méjì àwọn ará Ísírẹ́lì ní ìhà méjèèjì. Ísírẹ́lì sì pa wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì jẹ́ kí ọ̀kan kí ó yè tàbí kí ó ṣálọ nínú un wọn.

23. Ṣùgbọ́n wọ́n mú ọba Áì láàyè, wọ́n sì mu-un tọ Jósúà wá.

24. Nígbà tí Ísírẹ́lì parí pípa àwọn ọkùnrin Áì ní pápá àti ní ihà ní ibi tí wọ́n ti lépa wọn lọ, nígbà tí wọ́n pa gbogbo wọn tan, gbogbo àwọn Ísírẹ̀lì sì padà sí Áì, wọ́n sì pa àwọn tí ó ṣẹ́kù síbẹ̀.

Ka pipe ipin Jóṣúà 8