Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 7:2-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Jóṣúà rán àwọn ọkùnrin láti Jẹ́ríkò lọ sí Áì, tí ó sún mọ́ Bẹti-Áfẹ́nì ní ìlà-oòrùn Bétélì, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ gòkè lọ kí ẹ sì ṣe amí.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn arákùnrin náà lọ, wọ́n sì yọ́ Áì wò.

3. Nígbà tí wọ́n padà sí ọ̀dọ̀ Jósúà, wọ́n wí pé, “Kì í ṣe gbogbo àwọn ènìyàn ni ó ni láti gòkè lọ bá Áì jà. Rán ẹgbẹ̀rún méjì tàbí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti gbà á, kí ó má ṣe dá gbogbo àwọn ènìyàn ní agara, nítorí ìba ọkùnrin díẹ̀ ní ó wà níbẹ̀.”

4. Bẹ́ẹ̀ ní àwọn bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin lọ; ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Áì lé wọn sá,

5. wọ́n sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Ísírẹ́lì láti ibodè ìlú títí dé Ṣébárímù, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pámi.

6. Jósúà sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojú bolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Ísírẹ́lì sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí i wọn.

7. Jósúà sì wí pé, “Háà, Olúwa Ọlọ́run alágbára, nítorí i kiín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá a Jọ́dánì, láti fi wọ́n lé àwọn ará Ámórì lọ́wọ́; láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdì kéjì Jọ́dánì?

8. Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Ísírẹ́lì sì ti sá níwájú ọ̀ta a rẹ̀.?

Ka pipe ipin Jóṣúà 7