Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 24:24-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Jóṣúà pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọràn sí.”

25. Ní ọjọ́ náà Jóṣúà dá májẹ̀mu fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Sékémù.

26. Jóṣúà sì kọ gbogbo ìdàhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi Óákù ní ẹ̀bá ibi-mímọ́ Olúwa.

27. “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòtítọ́ sí Ọlọ́run yín.”

28. Lẹ́yìn náà ni Jóṣúà jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀-ìní rẹ̀,

29. Lẹ́yìn nǹkàn wọ̀nyí, Jóṣúà ọmọ Núnì ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún (110)

30. Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Tíminátì Sérà ni ilẹ̀ orí òkè Éfúráímù, ní ìhà àríwá Òkè Gááṣì.

31. Ísírẹ́lì sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Jóṣúà àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbààgbà tí ó pẹ́ ju Jóṣúà lọ àti àwọn tó ti rí ohun gbogbo tí Olúwa ti ṣe fún Ísírẹ́lì.

32. Egungun Jóṣéfù, èyí tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kó kúrò ní Éjíbítì, ni wọ́n sin ní Ṣékémù ní ìpín ilẹ̀ tí Jákọ́bù rà fún ọgọ́ọ̀rún (100) fàdákà ní ọwọ́ Hámórì, baba Ṣékémù. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀-ìní àwọn ọmọ Jósẹ́fù.

33. Élíásérì ọmọ Árónì sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gíbéà, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Fínéhásì ní òkè ilẹ̀ Éfúráímù.

Ka pipe ipin Jóṣúà 24